Àwọn olóṣùgbó yarí ní Ijebu-Ode lórí ìsìnkú Awujale, wọ́n fi ìlànà lélẹ̀ fún ọba tó kàn

Àkọlé fídíò,
Àwọn olóṣùgbó yarí ní Ijebu-Ode lórí ìsìnkú Awujale, wọ́n fi ìlànà lélẹ̀ fún ọba tó kàn

Agbarijọpọ awọn oṣugbo niluu Ijẹbu-Ode, nipinlẹ Ogun, ti ṣe iwọde lori bi wọn ko ṣe sin oku Awujale Ijebu, Ọba Sikiri Adetona, to waja laipẹ yii.

Ọjọ Aiku, ọjọ kẹtala oṣu Keje, ọdun 2025 ni oriade naa darapọ mọ awọn babanla rẹ, lẹyin to ti lo ọdun marundinlaadọrin lori itẹ.

Bi iku rẹ ṣe dun ọpọ ọmọbibi ilẹ Ijẹbu, naa lo tun fa awuyewuye laaarin awọn kan.

Eyi ni ko ṣẹyin bi awọn Alfa ẹlẹsin musulumi ṣe sinku ọba naa, tako ireti ọpọ eeyan pe, awọn alawo ni yoo sinku rẹ.

Lati igba naa si ni ọrọ ọhun ti n fa wahala ati ifẹhonuhan lati ọdọ awọn ẹgbẹ ẹlẹsin ibilẹ loriṣiriṣi.

Awọn obinrin Osugbo to n ṣe iwọde. Wọn wọ aṣọ ankara oriṣi kan naa, wọn si we gele lasiko ti wọn duro niwaju aafin Olu-Isa

Ọkan lara awọn ẹgbẹ naa to tun ti jade bayii ni awọn Osugbo, pẹlu iwọde ti wọn ṣe.

Ninu ifọwọwerọ pẹlu BBC News Yoruba, olori ẹgbẹ naa, Folashade Olowolayemo, sọ pe ko boju mu bi wọn ko ṣe pe awọn sibi isinku ọba naa.

O ni dandan ni ki Awujale tuntun fọwọ si iwe adehun pẹlu awọn, eyi ti yoo ni ibuwọlu Agba Agbẹjọro, pe oun gba

Bakan naa ni Oshotegun Alawiye, Iya Oriṣa ilẹ Ijẹbu sọ pe, Awujale tuntun gbọdọ ṣe iwe fun gbogbo awọn oniṣẹṣe pe, oun ko ni doju iṣẹṣe delẹ.

Ẹwẹ, ẹnikan lara awọn olori ilu, Emmanuel Ademuyiwa naa sọ pe, dandan ni igbesẹ naa jẹ bayii, "ẹni ti ko ba si ti le ṣe e , ko ni i le jọba".

Ṣugbọn ṣa, Lisa ti ilu Ijebu-Ode, Ọba Rasheed Adesanya sọ pe lootọ ni ijọba ti ṣe ofin pe, ọba lẹtọọ lati yan ẹsin to ba fẹ ko sin oku rẹ, o ni amọ ki iru ọba bẹẹ ṣe eto to yẹ lati mọ riri tabi fun awọn oniṣẹṣe ni nnkan to tọ si wọn lasiko isinku