You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
APC Aspirants Screening: Wo ọjọ́ tí ìgbìmọ̀ àyẹwò yóò bẹ̀rẹ̀ iṣẹ lórí àwọn olùdíje tí wọn fí fọ́ọ̀mù ṣọ̀wọ̀ fun ipò labẹ àsìá APC
Oludije mọkandinlọgbọn ni o ti n jọ pe wọn ti fi fọọmu wọn ṣọwọ ti wọn yoo sì lè koju igbimọ ayẹwo ẹgbẹ oṣelu APC .
Laarin ọjọ meji ni wọn yoo fi se ayẹwo yí ṣaaju idibo abẹnu ẹgbẹ ni ọjọ kejidinlọgbọn osu kaarun.
Lara awọn to ribi fi fọọmu wọn ṣọwọ la gbọ pe igbakeji ààrẹ Yemi Osinbajo ati Asiwaju Bola Tinubu wa.
- Ó dàbí ẹni pé ẹ kò mọ̀ ìdí tí mo fi ń díje dupò ààrẹ, òhun rè é - Tinubu ṣàlàyé
- Ìdí mọ́kànlá nìyìí tí mo fi fẹ́ díje dupò ààrẹ ní Naijiria – Bukola Saraki
- Ngige kọrin tuntun mi ò díje dupò aàrẹ Nàìjíríà mọ́, mo ti padà sí ọ́ọ́fíìsì mínístá tí mo wà tẹ́lẹ̀
- Fífún ẹkùn tàbí ẹ̀yà kan ní tíkẹ́ẹ̀tì 'zoning' kò sí nínú òfin ẹgbẹ́ wa - PDP
- Báwo ni ọ̀rọ̀ ilé ṣe fa Gbas-gbos láàrín Mercy Aigbe, ìyáále rẹ̀ àti ọkọ rẹ̀?
- Human Rights Watch fẹ̀sùn àìbìkítà kan ìjọba Naijiria lẹ́yìn ikú awọn olùwọ́de lásìkò ìwọ́de EndSARS
- Ìjọba Oyo dá ẹ̀kọ́ nípa ìmọ̀ ìtàn "History" padà sí ilé ẹ̀kọ́ alákọ̀bẹ̀rẹ̀
- Olùkọ́ Chrisland College mẹ́rin fojú balé ẹjọ́ lórí ẹ̀sùn ìbálòpọ̀
Bẹẹ naa ni ààrẹ Banki idagbasoke ilẹ Afrika,Dokita Akinwumi Adesina, Ogbonnaya Onu to jẹ mínísítà fun eto imọ ẹrọ ati sayensi ni Naijiria tẹlẹ ati aarẹ ile igbimọ aṣofin agba, Naijiria, Ahmad Lawan.
Amọ,a ko le fidi ọrọ múlẹ boya ààrẹ tẹlẹ rí Goodluck Jonathan ati Gomina banki apapọ Godwin Emefiele tàwọn kan ra fọomu fún ribi fi tiwọn ṣọwọ ṣaaju gbedeke ago mejila oru ọjọ Ẹti.
Yatọ sí àwọn taa ka kalẹ yi awọn oludije miran ti wọn ti fi fọọmu wọn ṣọwọ niyi:
- Pasitọ Tunde Bakare
- Rotimi Amaechi
- Godswill Akpabio
- Sen Rochas Okorocha
- Sen Ibikunle Amosun
- Gómìnà David Umahi
- Gómìnà Kayode Fayemi
- Gomina Yahaya Bello ati awọn miran.
Ọjọ wo ni igbimọ ayẹwo yoo bẹrẹ iṣẹ?
Atẹjade kan lati ọdọ akọwe eleto igbimọ ayẹwo APC, Suleiman Muhammad Argungu sọ pe wọn yoo ṣe ìfilọ́lẹ̀ awọn alaga ati akọwe igbimọ fún ipo ile aṣofin ati Gomina ni ọjọ Abameta tii se ọjọ kẹrinla oṣù Kàrún.
O ni kete ti ìfilọ́lẹ̀ yi ba ti pari ni awọn alaga ati akọwe igbimọ naa yoo bẹrẹ iṣẹ ayẹwo àwọn tó fẹ du ipo ile asoju sofin mu.
Ọjọ Kejì ọjọ yi ni tàwọn tó fẹ du ipo Gomina ati ile aṣofin agba yoo tẹle.
- Kìí ṣe àwọn mínísítà tó fẹ́ dupò nìkan ní Buhari ní kó fi iṣẹ́ sílẹ̀ , wo àwọn tó tún kàn
- Ṣé lóòtọ́ ní Makinde gbà tíkẹ̀ẹ̀tì Sẹ́nétọ̀ lọ́wọ́ Kola Balogun fún Joseph Tegbe?
- Ilé tí mo kọ́ ni Ìlànà Omo Oòduà, mi ò lè sá kúrò níbẹ̀ - Ọ̀jọ̀gbọ́n Banji Akintoye
- Àsìkò ti tó kí ìjọba fihàn pé kò sẹ́ni tó kọjá òfin lórí ikú Deborah- Ẹgbẹ́ Mususlumi ní Nàìjíríà
- Ìdí mẹ́ta tí Goodluck Jonathan kò fi lè díje dupò lábẹ́ ẹgbẹ́ òṣèlú kankan lásìkò yìí
- Wo ìdí tí Ilé aṣòfin àpàpọ̀ Nàìjíríà ṣe yí òfin ìdìbò padà fún ààrẹ, gómìnà, àwọn aṣòfin àtàwọn míràn
- Kò sí akẹ́kọ̀ọ́ ìpínlẹ̀ Sokoto, Zamfara tí yóò ṣe ìdánwò WASSCE lọ́dún 2022
- Wo àwọn obìnrin mẹ́wàá tí ipa wọn kò ṣe fọwọ́ rọ́ sẹ́yìn ní ààfin Oyo
- Ṣé lóòtọ́ ni Jonathan ti gbẹ̀yìn darapọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ APC? Nkan tí PDP àti APC sọ rèé
A kò ti ni iroyin to se dimu lori igba ti ìfilọ́lẹ̀ àti ayẹwo igbimo tàwọn tí yoo du ipò ààrẹ yoo waye.
Amo igbakigba ti yoo ba jẹ, iṣẹ tó pọ ni igbimọ naa yoo ṣe nítorí iye àwọn oludije ipo ààrẹ labẹ asia ẹgbẹ APC kii ṣe kekere.