Idaho School Shooting; Ọmọ ọdún mọ́kànlá yìnbọn mọ́ èèyàn mẹ́ta níléèwé

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ọmọdebinrin kan tii se ọmọ ọdun mọkanla si mejila ni iroyin lo yinbọn lu awọn akẹgbẹ rẹ meji ni ileewe ati tisa ni ipinlẹ Idaho, lorilẹede Amẹrika.
Ileeṣẹ ọlọpaa nipinlẹ naa ni ọmọdebinrin ti wọn ko darukọ rẹ ọhun wa ni ipele kẹfa ni ileewe alakọbẹrẹ.
Ọmọdebinrin ọhun lo mu ibọn lọ si ileewe Idaho Middle School to si ṣina bolẹ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Mide ṣèrántí ikú ìyá rẹ̀, Salawa, Bukunmi, Ninalowo ṣọjọ́ ìbí...
- Ẹbí Adeboye kéde bí ìlànà ikú Pásítọ Dare yoo ṣe lọ
- Ikú Dare Adeboye kò ní ǹkankan ṣe pẹ̀lú Covid-19, a bẹ̀bẹ̀ láti dá wà lákòókò yìí - Ẹbi Adeboye
- Àwọn ǹkan tí o kò gbọ́ rí nípa Dare Adeboye tó kú
- Mo dákú rangbọndan lẹ̀yìn tí amúgbálẹ́gbẹ gómìnà Akeredolu fún mi ní ìgbájú olóyì - Aláboyún
- Iléẹjọ́ pàṣẹ pé kí Makinde san N20m lórí bo ṣe dáwọn alága káńsù APC l'Oyo dúró lọ́nà àìtọ́
- Ọba Tejuosho tẹ ojú lọ́balọ́ba mọ́lẹ̀ fún ṣíṣe jìbìtì ìfẹ́ orí ayélujára - Ìgbìmọ̀ Afọbajẹ
- Ẹbí Fela Anikulapo yarí fún APC àti Tinubu torí èròjà ìpolongo ìbò
Eniyan mẹta to faragba ninu iṣẹlẹ naa ni awọn alaṣẹ sọ wi pe wọn ko ku, amọ wọn farapa.
Ọpẹlọpẹ olukọ obinrin miran lo jijakadi pẹlu ọmọdebinrin naa, to si gba ibọn lọwọ rẹ, ki awọn ọlọpaa to de lati fi panpẹ si lọwọ.

Ko tii han si ẹnikẹni idi ti ọmọ naa fi yinbọn lu akẹgbẹ ati olukọ rẹ.
Awọn ti iṣẹlẹ naa ṣoju wọn ni n ṣe ni ọmọdebinrin naa yọ ibọn kuro ninu baagi to gbe pọn, to si bẹrẹ si yin ibọn leralera ninu ileewe naa ati ita.
Bẹẹ si ni wọn bẹrẹ si ni gbọ ariwo kikan kikan lẹyin ti awọn to faragba ninu iṣẹlẹ naa ṣiṣe.
Adari ileewe naa, Chad Martin ni ibanujẹ ọkan ni iṣẹlẹ to waye ni ileewe wọn jẹ fun gbogbo awọn ti ọrọ naa kan, amọ wọn dupẹ pe ko mu ẹmi ẹnikẹni lọ.
Bakan naa ni wọn ti paṣẹ lati ti ileewe naa pa ni Ọjọ Ẹti, amọ awọn olubadamọran yoo wa ni ikalẹ lati ba awọn akẹkọọ sọrọ.
Ileeṣẹ ọtẹlẹmuyẹ lorilẹede Amerika, FBI ati ọlọpaa abẹlẹ ni iwadii ti bẹrẹ ni pẹrẹwu lori iṣẹlẹ naa.













