You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Fulani-Yoruba Crisis: Àwọn oníṣòwò Hausa ti ń kó ọjà wọlé padà- Aminu Alaba Rago
BBC ti fidiẹ mulẹ pe awọn ọja ounjẹ ti pada n wọle bayii lati ariwa Naijiria wa si Iwọ oorun guusu ati ila oorun guusu.
Saaju ni awọn Ẹgbẹ Amalgamated Union of Foodstuff and Cattle Dealers of Nigeria (AUFCDN) ti kọkọ gunle iyanṣẹlodi Ọlọrun má jẹ́ kí a jẹ́ gbèsè lókù báyìí tí a kò kó ọjá lọ sílẹ̀ Yorùbá mọ́- Hausa Oníṣòwò
Iyanṣẹlodi yii mu nkan bajẹ lori igba ati ninu ọkọ awọn oniṣowo Hausa ni eyi to jẹ ki awọn eeyan Yoruba ma ra ounjẹ bii Tomati, alubosa, Ewa, Agbo ati bẹẹ bẹẹ lọ lowo gọbọi.
Lẹyin ipade loriṣiiriṣii ni wón wọgile iyanṣẹlodii naa lẹyin ti wọn fẹnuko lori awọn nkan kọọkan.
Alaga ẹgbẹ Amalgamated Union of Foodstuff and Cattle Dealers of Nigeria (AUFCDN), ẹka Alaba Rago, Alhaji Aminu lo fidiẹ mulẹ fun BBC pe ọja ti n wọle si ipinlẹ Eko atawọn ipinlẹ to kù.
O ni gbogbo awọn ọkọ akẹru ati tirela ti wón da duro tẹlẹ ni oju ọna ni ipinlẹ Kwara ati Niger ni awọn ti ri ti wọn ti n kọja wọle bayii.
Gbogbo ọja to ha si opopona tẹlẹ ti wọ awọn ipinlẹ ile Igbo ati ti ilẹ Yoruba.
- Báwo ní Ọba Rilwan Akiolu tí ìlú Eko ṣe ní $2 million àti N17 million sí inú àfin rẹ̀?
- Baba tó dàbí MC Oluomo láyé yìí kò sí, ẹni tó bá níi, ó ní ohun gbogbo- Ọmọ MC Oluọmọ
- Àwọn ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa Sadiq Daba 'Inspector Waziri' nínú sinimá October 1 tó jáde láyé rèé
- Àwọn ará abúlé kan ṣàwàrì àlùmọ́ọ́nì gòólù ní wọ́n bá kígbe síta ní Ọlọ̀pàá bá yi wọn ká!
Saaju ni awọn oniṣowo Hausa ti a ba sọrọ ti fi aidunnu han lori awọn nkan ti wọn padanu tẹlẹ.
Wọn ni awọn nkan ti awọn naa padanu ka wọn lara ṣugbọn aabo ẹmi ati dukia koowa lo jẹ gbogbo eeyan logun
Ìjà ti parí, a ti gbà láti má a gbé ounjẹ wá sí ilẹ̀ Yoruba padà'- Hausa-Fulani Ọlọ́jà
Egbe awọn agbẹ olounjẹ lati Ariwa orilẹ-ede Naijiria pẹlu awọn Fulani darandaran (AUFCDN) ti gbegile iyanṣẹlodi ti wọn gunle.
Ẹgbẹ Amalgamated Union of Foodstuff and Cattle Dealers of Nigeria (AUFCDN) naa ni awọn yoo bẹrẹ si ni gbe ounjẹ pada wa si Iwọ oorun orilẹ-ede Naijiria lasiko ipade pẹlu ijọba apapọ ti Gomina ipinlẹ Kogi, Yahaya Bello ṣe aṣoju fun ni ilu Abuja.
Ninu ọrọ tirẹ, gomina ipinlẹ Kogi, Yahaya Bello bẹ ẹgbẹ naa ki wọn fi opin si iyanṣẹlodi wọn, ti awọn yoo si ri daju pe gbogbo nkan ti wọn bere fun ni ijọba a fi fun wọn.
- Wọ́n tún yìnbọn níbi àpèjẹ ẹ káàbọ̀ tí wọ́n ṣe fáwọn akẹ́kọ̀ọ́bìnrin Zamfara lẹ́yìn àṣẹ Buhari
- Ọlọrun má jẹ́ kí a jẹ́ gbèsè lókù báyìí tí a kò kó ọjá lọ sílẹ̀ Yorùbá mọ́- Hausa Oníṣòwò
- Ẹ kó àwọn ọkọ̀ yín tó ti dẹnukọlẹ̀ kúrò lójú popo tàbí kí a gbẹ́sẹ̀lé wọn- FRSC sí àwọn awakọ̀
- Àwọn tó jí akẹ́kọ̀ọ́bìnrin gbé ní Zamfara fẹ́ yẹ̀yẹ́ Ìjọba Buhari ni- Hadi Sirika
- Wo ìtàn Orunmila, Babaláwo àkọ́kọ́ àti ohun tó fi sílẹ̀ lọ níbí
- Èèyàn 464 míràn ló ṣẹ̀ṣẹ̀ lùgbàdì Covid-19 ní Nàìjíríà
Gomina Bello ni gbogbo eniyan ni iyanṣẹlodi naa ta ba nitori awọn ọmọ Naijiria n la ọpọlọpọ idojukọ kọja nitori nkan to le, nitori naa ki wọn ma tun dakun iṣoro naa.
Aarẹ ẹgbẹ AUFCDN, Muhammed Tahir ni awọn gbe igbeṣẹ naa nitori ijọba gba lati san iye owo to le ni biliọnu mẹrin naira fun awọn fun gbogbo awọn nkan ti wọn padanu lasiko ija laarin awọn ẹya ni Naijiria.
Tahir ni ijọba ṣeleri lati ri pe aabo to daju wa fun wọn loju ọna ti wọn ba n gbe ounjẹ bọ lati Ariwa ati opin si bi wọn ṣe n gba owo gọbọi ni ọwọ wọn ni oju ọna.
''Inu wa dun nitori gbogbo nkan ti a bere fun ni ijọba gba lati ṣe fun wa.''
Tahir ni: ''Nitori ijọba ti Gomina Bello ṣoju fun bẹ wa wi pe awọn yoo ṣe ohun to tọ, ni awọn ṣe gbegile iyanṣẹlodi ọhun''
''Ijọba si ṣeleri lati pese aabo to tọ fun awọn ọlọja lati ariwa lati le ṣe iṣẹ wọn ni ọna to tọ''
- Wo ibi tí o ti lè fi orúkọ síìmù rẹ sílẹ̀ tàbí gba nọ́mbà tuntun tí síìmù rẹ bá sọnù
- Wo ohun tí Ńo-Fly Zone' túmọ̀ sí
- Ewú ńbẹ! tí ìjọba ìpínlẹ̀ bá sàkóso gbèndéke owó oṣù òṣìṣẹ́,wọ́n ò ní san N30,000, N10,000 ní wọ́n má á san -NLC
- Nǹkan dé, Igboho ní káwọn ọ̀dọ́ ilẹ̀ Yorùbá lọ múra ògùn jọ nítorí ohun tó ń bọ̀ lọ́nà
- Ohun tó yẹ kí ó mọ̀ nípa oríṣìíríṣìí ìlẹ̀kẹ̀ ìbàdí rè é
Bakan naa ni Minisita tẹlẹri fun ọrọ irinna ofurufu, Femi Fani Kayode ni Sunday Igboho ti fi da oun loju wi pe awọn Hausa-Fulani ko ni dojukọ ija ẹlẹyamẹya mọ.
Amọ, o kesi ijọba apapọ lati pese aabo to tọ fun awọn agbẹ naa ni ilẹ Yoruba nitori awọn Fulani darandaran to n pa awọn eniyan ninu igbo ijọba.
- Kí làwọn nǹkan tó lè rán ọkùnrin sí ọ̀run alákeji lásìkò ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin?
- Ẹ wo bí ìyàwó Pasitọ Adeboye ṣe sàpèjúwe rẹ̀
- Chimamanda Adichie pàdánù bàbá, ìyá láàrín ọdún kan, kíló ṣẹlẹ̀?
- Wo ìtàn Orunmila, Babaláwo àkọ́kọ́ àti ohun tó fi sílẹ̀ lọ níbí
- Nǹkan dé, Igboho ní káwọn ọ̀dọ́ ilẹ̀ Yorùbá lọ múra ògùn jọ nítorí ohun tó ń bọ̀ lọ́nà
- Àwọn ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ tó dá mi lọ́nà lọ́jọ́ Ẹtì fẹ́ pa mí ni -Sunday Igboho