You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Shiloh 2020: Oyedepo ní òun kò le tòṣì láéláé! Ẹni tó bá ń bínú kàn ń bínú lásán ni
Oludasilẹ ijọ Living Faith ti ọpọ mọ si Winners, Biṣọọbu David Oyedepo tun ti sọ pe oun ko le toṣi laelae!
Biṣọọbu Oyedepo sọrọ yii nigba ti o n waasu nibi akanṣe eto ọlọdọọdun ijọ Winners, Shiloh 2020 niluu Ota, ipinlẹ Ogun.
Biṣọọbu Oyedepo ni majẹmu ti Ọlọrun ti la kalẹ ninu iwe mimọ ti oun n tẹle ko le jẹ ki oṣi mọ ile oun laelae.
- Lóòtọ́ ni mo yìnbọn níbi yánpọnyánrin tó wáyé ládúgbò mi-Seun Kuti
- Ṣé lóòtọ́ọ́ làwọn ọlọ́ṣà tún gbẹ̀mí èèyàn kan ní Moniya, Ibadan?
- ''Buhari àti Tinubu ṣ'àdéhùn pé Yorùbá ni yóò jẹ́ olùdíje ipò ààrẹ APC lọ́dún 2023 ''
- Iléeṣẹ́ epo rọ̀bì ná ₦116m lórí báírò, ìwé ìkọ̀wé, àwọn aṣòfin fìka hánu
- Iléeṣẹ́ ológun ti yabo ibùdó àwọn jàndùkú tó jí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ gbé níléèwé katsina- Garba Shehu
O ṣalaye pe niwọn igba ti orun ba n yọ loke ti ilẹ si n su u, majẹmu to sọ oun di ọlọrọ ko le yipada laelae.
Biṣọọbu Oyedepo ni Ọlọrun sọ fun oun pe ilọrọ ninu Oluwa kii ṣe ileri, kii sii ṣe ọrọ adura ati aawẹ. Ti eeyan ko ba ko ipa tirẹ, Ọlọrun naa ko ni ṣe ohun kan.''
''Nigba naa ni mo ke Yeeeehhh! Mo o le toṣi laelae. Ẹni to ba fẹ lọrọ ninu Oluwa ko gbọdọ fi idamẹwa ati ififunni ṣere,'' Oyedepo lo sọ bẹẹ.
Ọlọrun tun sọ ohun miiran fun mi lẹyin ti mo ka iwe ti Kenneth ati Gloria Copeland lori ilọrọ ninu Oluwa tan.
Oyedepo ni: ''O sọ fun mi pe bi Oun ṣe maa n ṣi ferese ọrun si awọn eeyan naa ni Oun maa ṣi ferese ọrun sori ileeṣẹ.
Apẹẹrẹ iru rẹ to wa ninu Bibeli ni Abarahamu to san idamẹwaa lori gbogbo ohun to ko bọ lati oju ogun.
Biṣọọbu Oyedepo ni lati igba naa ni ijọ Winners ti bẹrẹ si ni san idamẹwaa eyi ti o si n jẹ ki ferese ọrun maa tubọ ṣi sori ijọ naa sii.
Ìjọ 10,000 tuntun ni a dá sílẹ̀ láì gba owó ọrẹ lọ́wọ́ ọmọ ìjọ lásìkò àrùn Coronavirus- Oyedepo
Oluṣọ agutan agba ijọ Living Faith, pasitọ David Oyedepo ti ṣi aṣọ loju eegun pe bo tilẹ jẹ arun Covid-19 ba gbogbo agbaye finra lọdun 2020, ẹka ẹgbẹrun mẹwaa tuntun ni ijọ naa ṣi lai gba kọbọ lọwọ ọmọ ijọ kankan.
Oyedepo lo sọ ọrọ naa lọjọ Abamẹta to jẹ aṣekagba ipade adura Shiloh, eyii to maa n waye lọdọdun.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, o ni "bo tilẹ jẹ pe arun naa n dun mọhuru mọhuru, ẹgbẹrun mẹwaa ẹka tuntun ni ijọ yii ṣi lai gba owo ọrẹ kankan, a o fi oju imu eṣu danrin."
- Owó Naira yóò sì tún padà níyì láwùjọ àwọn owó orílẹ̀-èdè tó gbé pẹ́ẹ́lí jùlọ lágbàáyé- Adeboye
- Igbo Olodumare rèé, níbi tí Ìgbín ti tóbi ju Ìjàpá lọ
- Àwọn jàndùkú agbébọn''jí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ lọ nílé ìwé girama Katsina'' lẹ́yìn tí Buhari gúnlẹ̀ sí bẹ̀
- Kí gan ló pa Dapo Ojora, ẹ̀gbọ́n ìyàwó Bukola Saraki l'Eko?
Nigba to n sọrọ ṣaaju nipa arun Covid-19, Oyedepe sọ pe oun ko gbagbọ pe Covid-19 kan wa nibi kankan .
O ni "ti wọn ba bere lọwọ mi nipa Covid-19, esi mi ko ju pe, Covid-19 wa, bẹẹ ni ko si."
- Wo oríṣìí àrùn márùn ún tí ìgbéyàwó láàrin ìbátan si ìbátan máa ń fà
- Sanwo-Olu, El-Rufai fara pamọ́ torí COVID-19 lẹ́ẹ̀kejì
- Iléeṣẹ́ epo rọ̀bì ná ₦116m lórí báírò, ìwé ìkọ̀wé, àwọn aṣòfin fìka hánu
- Agbébọn tún gbẹ̀mí àgbẹ̀ míì lọ́nà oko lágbègbè Ibarapa
- Àádọ́ta Náírà tí báńkì ń yọ nínú owó ìpamọ́ oníbàárà kò tọ̀nà - Iléejọ́
"Ẹni to ba gbagbọ ninu Covid-19 ni arun naa yoo ran, ẹni ti ko ba gbagbọ ninu rẹ ko ni lugbadi arun naa."
Lẹyin naa lo sọ siwaju si pe ọpọ eeyan lo ti ri iwosan gba lọwọ arun Covid-19 ninu ijọ oun.