Yemi Osinbajo: Osinbajo wọ́gilé ìrìn-àjò rẹ̀ lẹ́yìn tí ọ̀kan lára ẹ̀ṣọ́ rẹ̀ kú lọ́nà pápákọ̀ òfurufú

Oríṣun àwòrán, Twitter/Prof Yemi Osinbajo
Ọkan lara awọn ẹṣọ igbakeji aarẹ, Ọjọgbọn Yemi Osinbajo ṣagbako iku ojiji ninu ijamba alupupu lọjọ Ẹti.
Ali Gomina, to jẹ ọlọpaa insipẹkitọ gbẹmi mi ninu ijamba naa to ṣẹlẹ lọna papakọ ofurufu Nnamdi Azikiwe niluu Abuja.
Gẹgẹ bi ọrọ ti oludamọran igbakeji aarẹ lori ọrọ iroyin, Laolu Akande sọ, Gomina wa lara awọn ẹṣọ to n sin igbakeji aarẹ lọ nigba ti iṣẹlẹ buruku naa ṣẹlẹ.
- Ọkùnrin tó bẹ́ sì òdò ọ̀sà pa ọ̀rẹ́bìnrin rẹ̀, lòun náà fi fẹ́ kú - Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá
- Kò sẹ́ni tó fẹ́ pa Buhari o, ọkùnrin tó pakuru mọ́ ààrẹ kàn fẹ́ bọ̀ọ́ lọ́wọ́ ni - Femi Adesina
- Yorùbá rẹwà, kọ́ nípa àwọn ọ̀rọ̀ tí ìró ẹnu wọn jọra àmọ́ tí ìtumọ̀ wọn yàtọ̀
- Àríwá Nàíjíríà, ẹ sọ ẹran jọ̀bọ̀-jọbọ nù pẹ̀lú Sanusi tẹ yọ lóyè - Soyinka gbarata
- Coronavirus tún ti bẹ́ gìjà sí Ghana àti Gabon
- Ẹ yọmí kúrò ní àhámọ́! Sanusi pe Ọ̀gá ọlọ́pàá àti Ọ̀gá DSS lẹ́jọ́
Ọgbẹni Akande ṣalaye pe igbakeji aarẹ ti wọgile irin-ajo to fẹ rin naa lẹyin iku ọlọpaa ọun to jẹ ẹni ọdun mẹẹdọgbọn.

Oríṣun àwòrán, Twitter/Prof Yemi Osinbajo
Ọjọgbọn Osinbajo ṣapejuwe oloogbe naa gẹgẹ bi ẹni to jara mọ iṣẹ to ṣi ṣe fi ọkan tan an.
Gomina fi iyawo atawọn ọmọ silẹ lọ, oludamọran igbakeji aarẹ gbadura pe ki Eleduwa tẹ ẹ si afẹfẹ rere.








