Ẹ má mu gaarí mọ́ nítorí ìbà Lassa- Dókítà Boniface

Oríṣun àwòrán, @Others
Adari ẹka eto ilera ni ipinlẹ Enugu, Oniṣegun oyinbo Boniface Okolo ti kilọ fawọn eniyan Naijria.
O ni iwadii ti fihan pe lara gaari ni awọn ekute ile ti maa n tan arun iba Lassa kalẹ.
Okolo fi ikilọ yii sita lasiko to n ni ifọrọwanilẹnuwo pẹlu ileeṣẹ iroyin Naijiria (NAN) nilu Enugu.
O ni o ti di dandan ki eleto ilera kilọ fawọn ara ilu lori ipa ti ekute ile ati gaari n ko ninu itankale Iba Lassa.
Dokita Okolo ni o ṣe pataki lati kilọ nipa mimu gari lasiko yii nitori pe wọn kii fi omi gbigbona muu bi ẹba.
Dokita Boniface ni omi gbigbona ti wọn n fi si ẹba fi tẹẹ a maa pa kokoro arun lassa ninu gaari ṣugbọn omi tutu ko ni pa kokoro naa ti awọn eeyan ba fi mu gari.
Dokita ni o san lati fi gari tẹ ẹba ju lati muu lọ nitori itankalẹ arun iba lassa yii.
- Ìgbéyàwó ọkùnrin s'ọ́kùnrin, obìnrin s'óbìnrin ti di òfin ní Northern Ireland
- Wo àwọn krìstíẹ́nì tó n wẹ̀ nínú odò tó ní yìnyín láti ṣàjọyọ̀ ìrìbọmi Jesu
- Ààfá mẹ́ta réwọ̀n hé nípa ṣíṣe ìrànlọ́wọ́ òjijì fún obìnrin kan pẹ́lù 36 mílíọ̀nù náìrà
- Harry àti Meghan kò ní lo orúkọ oyè wọn mọ́, wọn kò sì lẹ́tọ̀ọ́ sí owó ilú mọ́ ní UK
O ni awọn oṣiṣe eleto ilera n gbiyanju lati gbogun ti itankalẹ arun buruku yii paapaa nipinlẹ Enugu ṣugbọn gbogbo ara ilu gbọdọ fọwọsowọpọ lati ja ija ilera naa yanju ni.
Bakan naa lo tun kilọ pe ki awọn eeyan ma fọ eso ati ewebẹ wọn daadaa ki wọn to jẹẹ.
Ni ipari o ni ki onikaluku ṣọra lori ọna ti wọn n gab fi ounjẹ pamọ ki ekute ile ma ti lọ tẹnu bọọ ki wọn si ko arun Lassa sinu ounjẹ naa.
O ni ki awọn eeyan maa lo ike ọlọmọri to de daadaa ki wọn to fi ounjẹ silẹ ninu ikoko lai dee daadaa.

















