Lagos State: Ẹbí èèyàn márùn ún àti àlejò kú sínú ilé l'Eko

Oríṣun àwòrán, Twitter/@sagagist
Igbe oro lawọn agbebe lawọn olugbe agbegbe Mafoluku l'Oshodi n ke l'Ọjọru lẹyin ti wọn ba oku eeyan meje pẹlu alejo wọn ninu ile laarọ Ọjọru.
Nọmba 19, Olowora ni awọn ara adugbo Mafoluku ti ri oku ọkunrin kan, ati iyawo rẹ pẹlu awọn ọmọ mẹrin ati alejo wọn ti oyun wa ninu rẹ.
Iroyin ti a gbọ ni pe iṣẹlẹ ọhun waye ninu yara kan tawọn eeyan naa sun si.
- Ìjọba Nàìjíríà ti ránsẹ pé àsoju ijọba ni South Africa láti dari wálé
- ShopRite Ibadan gbé ìlẹ̀kùn tìpa torí ìkọlù àwọn tó ń fẹ̀hónú hàn
- Ọlọ́pàá fi afẹ́fẹ́ tajú-tajú àti omi tú àwọn tó fẹ́ ṣun ilé ìtajà ShopRite l‘Abuja ká
- Àwọn èèyàn Gómìnà Yahaya Bello ló da ìbò abẹ́nú PDP rú- Ọlọgbọndiyan
- Wike kìí ṣe dọ́là tí Ganduje leè kó sápò- Agbẹ́nuso ìjọba ìpínlẹ Rivers
- Ọ̀pọ̀ èèyàn bẹnu ẹ̀tẹ́ lu Mercy Aigbe lórí bó ṣe ki Adeniyi Johnson
Ko si ẹni to mọ pato ohun to ṣe okunfa iku wọn ṣugbọn awọn kan ni o ṣeeṣe ki wọn jẹ majele mọ ọunjẹ.
Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Eko ko gbe ago nigba ti BBc Yoruba pe wọn lati mọ ohun to ṣokunfa iku awọn eeyan naa.








