Xenophobic Attack: Ìjọba rọ ọmọ Nàìjíríà pé kí wọ́n dẹ́kun kíkọlu iléeṣẹ́ South Africa

Awọn olufẹhonu han

Oríṣun àwòrán, Twitter/@Julisco

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 2

Okun kii ho ruru ka wa ruru! Bayii ni ijọba apapọ ṣe n parọwa fawọn ọmọ Naijiria pe ki wọn ye kọlu awọn ileesẹ to jẹ ti orilẹde South Africa to wa ni Naijiria lati gbẹsan iṣekupani awọn ọmọ Naijiria lorilẹde naa.

Ijọba ni kikọlu awọn ileeṣẹ orilẹede South Africa ni Naijiria yoo ni ipa ti ko dara lara ọmọ Naijiria ju South Africa lọ.

Minisita fun iroyin ati aṣa, Alhaji Lai Mohammed sọ ninu atẹjade kan pe bawọn ọmọ Naijiria kan ti fi ibinu kọlu awọn ileeṣẹ to jẹ ti orilẹede South Africa lọjọ Iṣẹgun ku diẹ kaato.

Lai Mohammed ni awọn ọmọ Naijiria ni oludokowo lawọn ileeṣẹ orilẹede South Africa, nitorinaa fifi ọwọ ara ẹni ṣera ẹni ni kawọn ọmọ Nigeria maa ba iru awọn ileeṣẹ bẹẹ jẹ.

Bakan naa ni minisita eto iroyin ati aṣa ni ọmọ Naijiria lo pọju ninu awọn oṣiṣẹ ileeṣẹ South Africa to wa ni Naijiria.

Skip X post, 1
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 1

Skip X post, 2
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 2

Skip X post, 3
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 3

O fikun ọrọ rẹ pe awọn ọmọ Naijiria lo maa fori ko ju, ti awọn ileeṣẹ orilẹede South Africa ba di titi pa.

Minisita Aarẹ Muhammadu Buhari ti ran awọn aṣoju si aarẹ South Africa lati fi ẹdun ọkan rẹ han ati lati wa nnkan ṣe si ikọlu ati ikoriira awọn ọmọ Naijiria to n gbe ni South Africa.

Awọn olufẹhonu han

Oríṣun àwòrán, Twitter/@Julisco

O ni aarẹ ti sọ fun minisita ọrọ ilẹ okere, Geoffrey Onyeama pe ko ranṣẹ pe aṣoju orilẹede South Africa ni Naijiria pe ko wa sọ tẹnu rẹ, bi o tilẹ jẹ pe aṣoju South Africa oun ti sọ pe ohun to n ṣẹlẹ kii ṣe ikoriira awọn ọmọ Naijiria.

Ẹwẹ, ẹgbẹ oṣelu alako PDP ti kepe ile igbimọ aṣofin agba l'Abuja lati pe ipade pajawiri lori ọrọ naa.

PDP bu ẹnu ẹtẹ lu ijọba Aarẹ Buhari pe ko tete ja ọrọ naa kunra, wọn ni o buru jai pe olu ileeṣẹ Naijiria to wa nilẹ South Africa tun kọ ẹyin si awọn ọmọ Naijiria to sa lọ sibi.