A kò fòfin de owó naira tó ti pẹ́ ní Naijiria- CBN

owo
Àkọlé àwòrán, Owo tuntun lo dun lati na

Ọpọ àwọn ọmọ Naijiria ni ẹru n ba lori iroyin to gba igboro kan pe banki apapọ Naijiria, CBN fẹ ko gbogbo owo atijọ nilẹ.

Eyi lo mu BBC kan si Mallam Aaron Musa, to jẹ ọga agba adari ọkan lara awọn banki olokowo Naijiria, iyẹn Guarantee Trust Bank (GTB) lori koko yii.

Mallam yii ṣalaye fun BBC pé aigbọraẹniye lo n yọ awọn eniyan lẹnu lori kiko owo ti ko daa mọ nilẹ.

Iwadii fihan pe awọn agbalagba kọọkan ti n ṣowo da gbese nitori wọn n ṣe paṣipaarọ owo wọn to ti dọti si tuntun ni odiwọn to keere niye.

Àkọlé fídíò, Ero ara ilu lori owo awọn sẹnatọ Naijiria

Mallam Aaron ni nitootọ ni banki Naijiria kede pe ki awọn gba awọn owo atijọ pada wọle ni gbendeke asiko kan.

O ni ṣugbọn aṣẹ yii ko ye awọn eniyan to ni.

O ni banki CBN gbe ero kan kalẹ lati ṣatunṣe si iye owo ti ijọba n na lapapọ ni igboro. ni eyi ti ero rẹ to miliọnu meji.

Adari banki GTB ṣalaye fun BBC pe banki CBN ti paṣẹ fun gbogbo banki pe wọn ko gbọdọ fun ẹnikẹni tabi ileeṣẹ kankan ni owo to dọti to jẹ owo atijọ mọ.

Àkọlé fọ́nrán ohùn, IMF gba Naijiria níyànjú lórí pàsípààrọ̀ owo Dola

O ni fun idi eyi, ẹni to ni owo ti ko dara mọ nile le koo lọ sile ifowopamọsi to ba wuu lati lọ ṣe paṣipaarọ rẹ si owo tuntun.

Erongba tuntun banki CBN yii ni ṣiṣe afọmo awọn owo Naijiria si eyi to dun lati wo loju.

Àkọlé fídíò, Ajọ SERAP sọrọ lori owo ifẹhinti awọn oloselu kan

Ni afikun, Mallam Aaron ni ofin wa fun gbogbo banki Naijiria lati paarọ awọn owo atijọ ti awọn eniyan ba ko wa.

O ni o di dandan ki banki tẹwọ gba awọn owo to ti ya tabi to ti dọti pa yii wọle ki wọn si fi owo tuntun sanwo fawọn onibara wọn sita.

Àkọlé fídíò, Ejo abami to n mu owo ni ajọ Jambu

Oludari yii ṣalaye pe banki CBN ni banki kọọkan a gba owo idapada N200:000:00 fun odiwọn oṣu mẹta ti wọn a fi maa ṣe eto yii.

O ni lẹyin gbendeke yii ni wọn yoo maa ri ẹgbẹrun mejila gba titi wọn yoo fi pari paṣipaarọ odiwọn owo banki kọọkan.

CBN

Oríṣun àwòrán, @CBN

Àkọlé àwòrán, Owó lowó n jẹ́, irọ ni pe a fẹ fofin de Naira to ti pẹ

Ogbontarigi nidi iṣẹ ifowopamọsi yii ni koda banki Naijiria ti yọ owo ori kuro fun oṣu mẹta fun gbogbo baniki ki awọn le ri koriya fun igbesẹ owo didọti gbigba wọle yii.

O ni koda iyekiye ti ẹnikẹni ba ni to dọti ni ki wọn ko lọ fun paṣipaarọ ni banki ki wọn le maa na owo naira tuntun.

O ni koda to ba wu ọ o le san owo atijọ naa si inu asunwọn rẹ ni banki tabi ki o tun fi ranṣẹ si ara rẹ pada.

Ni ipari, o rọ awọn ọmọ Naijiria tootọ lati ṣe itọju owo naira bi o ti yẹ.

O ni o wu gbogbo banki lati ṣatunṣe si bi awọn eniyan ṣe n ṣe owo naira Naijiria jakujaku.

Àkọlé fídíò, Ibikunle Amosun: Owo adani ni'ṣẹ ẹran dida, ko kan ijọba