Ghana Floods: Èèyàn méje pàdánú ẹ̀mí wọn nínú ìjàmbá ẹ̀kún omi

Awọn eeyan Ghana

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Àkọlé àwòrán, Ẹkun omi ni Ghana

Ojo arọọrọda ti gbẹmi eeyan meje niluu Accra tii ṣe olu ilu orilẹ-ede Ghana.

Lalẹ ọjọ Aiku lojo ọhun bẹrẹ ti o si rọ fun wakati mẹta gbako.

Nibi ti ajọ to n ri si ọrọ pajawiri lorilẹ-ede Ghana (NADMDO) ti n doola ẹmi awọn eeyan ni wọn ti ri oku eeyan mẹrin lagbegbe Ashaiman, bẹẹ ni wọn tun ri omiran lagbegbe Odorna.

Àkọlé fídíò, Colorado ni Amẹrika àti odò Awaye ní Naijiria nikeji àdágún órí àpáta ní gbogbo àgbáyé!

Igbakeji adari ajọ to n ri si ọrọ iṣẹlẹ pajawiri, Seji Saji to ba BBC sọrọ, fidi rẹ mulẹ pe awọn ri oku eeyan mẹrin to ku ninu ọkọ awọn ologun lagbegbe Adjei-Kojo.

Orilẹede Ghana

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Àkọlé àwòrán, Omíyalé gbẹ̀mí èèyàn méje, o tún ba dúkìá púpọ̀ jẹ́

O ṣalaye pe awọn eeyan naa sa wọ inu ọkọ ologun lati sa asala fun ẹmi wọn ni, ṣugbọn eyi ko da iku wọn duro.

Àkọlé fídíò, JAMB 2019: A ó fagi lé ìdànwò ẹni tó bá ṣe aṣemáṣe

Iroyin kan tiẹ sọ pe ina mọnamona gbe awọn kan ninu awọn eeyan to ku nigba ti awọn mii si rì somi.

Àkọlé fídíò, Segalink:ìkùnsínú pọ̀ láàrin àwọn agbófinró bẹ́ẹ̀ wọn kò ni agbẹnusọ

Ṣugbọn ajọ NADMDO ni iwadii si n lọ lọwọ lori iṣẹlẹ ẹkun omi naa.

Àkọlé fídíò, Ọ̀dọ́kùnrin tó kọ́kọ́ ṣe ẹ̀rọ tó ń tu ìyẹ́ lára adìyẹ