Àjọ̀dún APC lónìí, E wo ẹnu ilẹ̀, ẹ wo ẹnu ọkọ́ ni báyìí

ami ipade APC

Oríṣun àwòrán, @gloria-adagbon

Àkọlé àwòrán, Gbogbo ètò ń tò fún àjọ APC loni nilu Abuja

Ẹgbẹ́ òṣèlú APC tó ń tukọ̀ Nàìjíríà báyìí fẹ́ yan àwọn olóyè míràn.

Àwọn igba din lẹgbẹrun meje aṣoju ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress kaakiri Naijiria ni wọn yoo dibo loni.

Ọpọlọpọ ọmọ ẹgbẹ lati ipinlẹ mẹrindinlogoji Naijiria ni wọn ti jade lati dije du ipo mejilelogoji to ṣi silẹ loriṣirisi.

Ipo fún ogun eniyan ni wọn ko ni alatako rara nigba ti wọn yoo yan ẹni to wu wọn si awon ipo to ku.

Eto idibo naa yẹ ko waye loni lasiko ajọdun ẹgbẹ oṣelu APC nilu Abuja ni eyi ti o han pe gbogbo eto ti to ko le bẹrẹ lasiko.

Àkọlé fọ́nrán ohùn, Lori lẹta Obasanjọ

O ti hande pe Adams Oshiomole lati ipinlẹ Edo ni yoo rọpo John Oyegun gẹgẹ bii alaga gbogboogbo.

Awọn ipo nlanla to ṣi silẹ ni ti:

  • Igbakeji alaga fun ẹkun Ariwa, eyi ti Lawali Shuaibu, (Zamfara), to jẹ ọmọ ọdun mẹtalelogota ati Farouk Adamu Aliyu (Jigawa) to ti ṣoju ẹkun rẹ nile igbimọ aṣofin ri jọ n dù.
  • Igbakeji alaga fun ẹkun Guusu, ti Adeniyi Adebayọ (Ekiti) ṣeeṣe ko rọpo Segun Oni to dipo naa mu ninu ẹgbẹ tẹlẹ. (Sẹgun Oni fipo naa silẹ ko le raaye lọ dije fun ipo gomina nipinlẹ Ekiti).
  • Akọwe agba fun ẹgbẹ, eyi ti wọn gbe si ẹkun ariwa ila oorun Naijiria. Ogbeni Mai Mala Buni (Yobe) to kọkọ wọle sipo yii lọdun 2014 niroyin ni o ṣeeṣe ko tun pada sipo naa.
  • Bakan naa ni Ogbeni Kashim Imam (Borno) to ya kuro lẹgbẹ oṣelu PDP tẹle naa n lọ fun ipo Akowe agba fun APC.
  • Ogbeni Gambo Lawan (Borno) ni ẹni kẹta to n dije fun ipo akọwe ẹgbẹ APC ninu ajọdun oni.
  • Waziri Bulama to ya lati ẹgbẹ oṣelu CPC tẹlẹ naa tun n dije fun ipo akọwe kan naa.
  • Abdulrahman Terab (Borno) paapaa n dije fun ipo akowe APC pẹlu.
  • Fun ipo Alukoro ẹgbẹ, eyi ti wọn gbe si ẹkun aarin gbùngbùn ariwa Naijiria, Ogbẹni Bolaji Abdullahi (Kwara) to wọle sipo naa loṣu kejila, ọdun 2016 rọpo Oloye Lai Mohammed tun fẹ lọ lẹẹkan sii.
  • Duro Meseko (Kogi) to ti ṣe aṣoju ri naa n dije fun ipo alukoro APC.
  • Abubakar Sidiq Umar (Kogi) naa n dije fun ipo kan naa.
  • Lanre Issa-Onilu (Kwara) ni ẹni kẹrin lati ẹkun aarin gbungbun ariwa to n dije fun ipo Alukoro ẹgbẹ oṣelu APC.

Ìran ni ounjẹ ojú lonii, ki a maa wo ibi ti adé idibo àwọn ipò to ṣi silẹ fún idibo naa yoo ṣi si.

Àkọlé fídíò, Kola Ologbodiyan: Jẹgudu jẹra ni ijọba APC
Amin iyasọtọ kan

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Àkọlé fídíò, SARS ti bẹ̀rẹ̀ ìgbésẹ̀ láti yọ àwọn ọ̀bàyéjẹ́ kúro
Àkọlé fídíò, Onímọ̀ ọrọ̀ ajé: Àfíkún ìsúná táwọn asòfin se b‘ófin mu