Terhemen Anongo yọ kórópọ̀n rẹ̀ nítorí kí ara rẹ̀ má dìde láti lè bá obǹrin sùn

Oríṣun àwòrán, The PUNCH
Ọkùnrin kan, Terhemen Anongo, ẹni ọdún mẹ́rìnlélógójì tí kò lè tẹ̀síwájú nínú ẹ̀kọ́ ìmọ̀ ìṣègùn òyìnbó ní ipele karùn-ún ní ilé ẹ̀kọ́ gíga fásitì Ìbàdàn ti yọ kórópọ̀n rẹ̀ kejì.
Ìwé ìròyìn The PUNCH tí kọkọ fi ìròyìn kan léde nínú oṣù kẹta ọdún 2021 nípa arákùnrin náà tó yọ kórópọ̀n rẹ àkọ́kọ́ lẹ́yìn tó di ẹni tó ń ti ọmọlanke látàrí àìlè tẹ̀síwájú nínú ẹ̀kọ́.
Anongo ní nítorí òun kò nì ìyàwó pẹ̀lú ìgbàgbọ́ òun nínú ẹ̀sìn àti ohun tí òun kà nípa Origen Adamantius tó jẹ́ adarí ẹ̀sìn nígbà kan rí ní Egypt ló fún òun ní ìwúrí láti tẹ ara rẹ̀ lọ́dà.
- Gbogbo àṣà àtijọ́ fún yíyàn Ọba, ṣíṣe ìsìnkú Ọba gbúdọ̀ dópin lónìí pẹ̀lú àṣẹ - Dapo Abiodun
- Ilé ẹjọ́ pàṣẹ kí wọ́n fi àwòrán Raheem Adedoyin léde láwọn ìwé ìròyìn lórí ikú Timothy Adegoke
- Irọ́ ni pé àwòrán CCTV ṣàfihàn bí Ramon Adedoyin ṣe pa Timothy Adegoke - Agbẹjọ́rò Adedoyin
- Ó ṣe! Ọmọ olóògbé Soun Ogbomosho náà tún dágbére fáyé
- Àwọn ológun padà sí ọgbà ẹ̀wọ̀n ní ìpínlẹ̀ Ondo; ìdí rèé
- Kìí ṣe ohun tí ojú kò rí rí tí ìyàwó mi bá ní owó jù mí lọ - Kolawole Ajeyemi
"Nígbà tí mo fẹ́ yọ kórópọ̀n àkọ́kọ́, ẹ̀jẹ̀ pọ̀ tó ya lára mi, èyí tó mú mi sá lọ sí ilé ìwòsàn fún ìtọ́jú".
Kìí ṣe ilẹ̀ Afíríkà ni mo wà nígbà tí mo kọ́kọ́ wá sílé ayé - àṣírí ọ̀rọ̀ tuntun rèé lẹ́nu Mummy G.O
"Ṣùgbọ́n nígbà tí mo fẹ́ yọ ẹlẹ́kejì, mo ti kẹ́kọ̀ọ́ níbi ti àkọ́kọ́, mo ṣe é dada. Ẹnìkan ń wá bámi tọ́jú rẹ̀".
Ó ní ìgbàgbọ́ òun nínú ẹ̀sìn ni òun fi yọ ọ́ àti pé àláfíà ni òun wà.

















