Lagos School Building Collapse: Iléèwé míràn tún dàwó ní ìpínlẹ̀ Eko

Ajọ oṣiṣẹ pajawiri nipinlẹ Eko, LASEMA ti kede pe Ileewe kan ti wo ni agbegbe Ile Epo Bus Stop, Iyana Ejigbo ni ipinlẹ Eko.
Agbẹnusọ fun ileeṣẹ LASEMA, Nosa Okunbor lo fi lede bẹẹ.
- Lẹ́yìn olóògbé Barrister àti Kollington, èmi làgbà kàn nínú iṣẹ́ orin Fuji- Obesere yarí
- Ọkọ̀ méjì jóná ráùráú níbi tí ọkọ̀ tó gbé bẹntiróò ti gbiná
- Wo bí ìfigagbágbá tani yòó di gómìnà Edo láàrin Obaseki àti Ize-Iyamu yóò ṣe lọ
- Yatọ̀ sí pé ó ṣe sọ́jà, tó tún jẹ́ ọkọ Oriṣabunmi, wo àwọn nkan tí o kò mọ̀ nípa Jimoh Aliu
Okunbor fikun pe ileewe girama ni ileewe ti iṣẹlẹ naa ti waye.

Bakan naa lo dupẹ pe opin ọsẹ ni iṣẹlẹ naa waye, ti ko si si awọn ekẹkọọ ni ileewe lasiko ti iṣẹlẹ naa waye.

Ajọ Pajawiri naa kesi awọn oṣiṣẹ rẹ ni agbegbe naa lati tete tara sasa lọ si ibẹ.

Ọpọlọpọ ile ibugbe lo ti wo ni ipinlẹ Eko lọpọ igba, to fi mọ awọn ileewe ati ileeṣẹ ati ibugbe.

Ti a ko ba gbagbe, Ọjọ Kọkanlelogun, Oṣu Kẹsan ni ijọba ipinlẹ Eko ni ki awọn ileewe ṣi pada lẹyin oṣu marun un ti wọn ti wa ni ile nitori ajakalẹ arun Coronavirus.








