Aṣòfin Adeyẹmọ nífẹ̀ẹ́ sí ètò ìdájọ́ àti òfin

Oríṣun àwòrán, Facebook/Adeyemo
Olórí ilé aṣòfin ìpínlẹ̀ Òyọ́, Michael Adeyẹmọ tó dagbere fáyé lówúrọ̀ ọjọ́ ẹtì lọ sí ilé ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ Òkè Àdó, Ìbàdàn.
Olóògbé Adeyẹmọ tẹ̀síwájú ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní ilé ìwé girama ti ìjọ sẹ̀lẹ́ Òkè Àdó, Ìbàdàn.

Oríṣun àwòrán, Facebook/Adeyemo
Olóògbé náà lọ sí fásítì ti ìlú Port Harcourt níbi t'óti gba oyè àkọ́kọ́ nínú ìdarí ètò ẹ̀kọ́ tí ó sì pegedé níbẹ̀.
Ògbẹ́ni Michael Adeyẹmọ nífẹ̀ẹ́ sí ètò ìdájọ́ àti òfin.
Eléyìí lọ́ jẹ́ kó lọ k'ẹ̀kọ́ láti di agbẹjọ́rò nìgbàtí ó gb'oyè amòfin ní fásítì ìlú Ibadan.

Oríṣun àwòrán, Facebook/Adeyemo

Oríṣun àwòrán, Facebook/Adeyemo
Họ́nọ́rébù Adeyemo bẹ̀rẹ̀ òsèlú ni ọdún 2007.
Ó ti fi ìgbàkan rí jẹ́ igbákejì alámòótó ní ilé aṣòfin ìpínlẹ̀ Òyọ́ ní sáà ilé tó kọjá lọ.

Oríṣun àwòrán, Facebook/Adeyemo
Òun ni aṣòfin àkọ́kọ́ tí àwọn ará Ìlà-oòrùn Ibarapa tí ó ń sojú yóò kọ́kọ́ dìbò yàn lẹ́ẹ̀mejì.
Olóògbé Adeyemo fi ìyàwó àti àwọn ọmọ sílẹ̀ lọ.












