Nọ́ọ̀sì alábẹ́rẹ́ tó ń fi èdè Yorùbá kọ́ aráàlú nípa ìlera wọn

Àkọlé fídíò, Nọ́ọ̀sì alábẹ́rẹ́ tó ń fi èdè Yorùbá kọ́ aráàlú nípa ìlera wọn
Nọ́ọ̀sì alábẹ́rẹ́ tó ń fi èdè Yorùbá kọ́ aráàlú nípa ìlera wọn

Nọọsi alabẹrẹ to kọṣẹmọṣẹ ni Adejọkẹ Ogunbiyi ohun to sọ ọ di gbajugba lori ayelujara ni bi o ti ṣe n kọ eto ilera ati iṣegun oyinbo.

Lori ayelujara, Nọọsi Tiwantiwa ni wọn maa n pe Nọọsi Adejọkẹ loju opo ayelujara, ko si si ọrọ ilera kankan ti kii sọrọ le lori lede Yoruba.

O ni idi ti oun fi pinnu lati maa kọ awọn eeyan nipa ilera pẹlu ede Yoruba ni wi pe oun gbagbọ pe yoo tubọ mu ki ọpọ nnkan ti idape wọn lede oyinbo mu ki ọrọ ilera naa da bi idan o tubọ ye awọn eeyan sii.

Aworan Nọọsi Tiwantiwa

Oríṣun àwòrán, Noosi tiwańtiwa/instagram

O fi kun un pe ọpọ igba lawọn eeyan maa n fẹ ki oun sọ nipa ogun ti wọn le lo fun ọrọ ilera ti oun ba ṣalaye lori ayelujara, ṣugbọn oun maa n fẹ ko ye wọn pe igbesẹ idanilẹkọ oun ko si fun mimu ki awọn eeyan dẹkun lilọ ileewosan bikoṣe lati le dari wọn si ile iwosan pẹlu idaniloju nipa ipenija ilera ti wọn ba n dojukọ.

Ninu ifọrọwerọ rẹ pẹlu BBC, o ni lilo ede yoruba lati kọ oun ti oun pẹlu fi oyinbo kọ, bi awọn eeyan kan to n gbọ ọ ṣe maa n faake kọri pe bi awọn ti ṣe maa n ṣe lati igba atẹyinwa ni ko si ohun ti oun le ṣe lati da a nu.