Hajiya Binta Balarabe Kubaus: Obìnrin kan rí ẹ̀wọ̀n ọdún mẹ́wàá he ní Kaduna lẹ́yìn tó lu jìbìtì ₦5.5m

Hajiya

Oríṣun àwòrán, other

Obìnrin kan ti ri ẹwọn ọdun mẹwàá he lẹyìn tó jẹbi ẹsun lílu jibiti ni Kaduna.

Adájọ M.T.M Aliyu lo ṣe idajọ náà fún un lẹyìn tí àjọ EFCC fẹsun lílu jibiti owo ti iye rẹ le ni mílíọ̀nù marun un kan an.

Ìròyìn ní inú oṣù Kẹjọ, ọdún 2020 ni afurasi naa hu ìwà òdaran ọhun.

Wọn ní ọ parọ fún okunrin kan, Yahaya Mohammed Idris, pe òun yóò ta ilẹ fún lọna ati gba owo lọwọ rẹ.

Wọn ní ohun tí Hajiya Binta Balarabe Kubaus, obinrin naa ṣe lodi si òfin ìwà ọdaran ipinlẹ Kaduna, eyiti wọn gbe kalẹ lọdun 2017.

Ẹwẹ, afurasi náà sọ níwájú adájọ pe lootọ ni òun ṣe sí òfin náà, ṣugbọn ki wọn fi ojú aanu wo oun.

Àkọlé fídíò, Ẹlẹ́wọ̀n: Ọgbà ẹ̀wọ̀n ni mo ti kàwé yege ní ìdánwò Jamb

Agbejoro Hajia Binta, Sule Shuahibu bẹbẹ lẹyin ti onibara rẹ gab pe oun jẹbi ẹsun naa.

Bó tilẹ jẹ pé afurasi naa ti sọ pé òun yóò dá owó náà padà fun okunrin to lu ni jibiti.

Àkọlé fídíò, Sikiru Alabi

Adájọ ni ko lọ fi ẹwọn ọdun mẹ́wàá jura, tabi ko san ẹgbẹrun lọnà ìgbà náírà owo itanran le\yin to ti setan sisan owo naa pada.

Ṣaaju ni ẹni tí Hajiya Binta Balarabe Kubaus, obinrin naa lu ni Jibiti ti kọkọ kọwe mọ ọ ni ọọfisi EFCC pé ayédèrú iwe ilẹ lọ fún òun kí ọrọ náà tó dé iwájú Adájọ.

Àkọlé fídíò, Evangelist Funmilayo Adebayo Mummy G.O: Ìgbà tí mo wà ní ìjọ́ba òkùnkùn, gbogbo ayé ló fẹ́

Orọ ilẹ ni wọn fi ṣe owo naa ni Kaduna ni eyi ti iwe ẹri wọn yatọ si ara wọn.