Sex for Marks: Aago 9.25 àárọ̀ ni olùkọ́ fi tipá bá akẹ́kọ̀ọ́ náà lòpọ̀ nínú ọọ́fìsì

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Yoruba ni ẹni to ba mọ isin jẹ, o yẹ ko mọ ipin oju rẹ yọ nitori ohun ti eeyan ba mọ jẹ, nii yo.
Bẹẹ lọrọ ri fun olukọ kan tẹlẹ ni fasiti Eko, Azeez Baruwa, tileeẹjọ giga Eko ni ko yara lọ na naju lọgba ẹwọn fun ọdun mọkanlelogun.
Ẹsun ti wọn fi kan Baruwa ni pe o fi tipa tikuuku ba ọmọbinrin kan, ẹni ọdun mejidinlogun lopọ, ẹni to n wọna bi yoo se wọle sinu ọgba ileeẹkọ naa.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Maryam Sanda pe ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn lóri ìdàjọ́ ikú
- ''Láìpẹ́, ìjọba ìpínlẹ̀ Eko yóò fi ǹkan tó dára míì rọ́pò Kẹ̀kẹ́ àti ọ̀kadà''
- Ìhàlẹ̀ lásán ní NURTW ń ṣe torí pé a dínà owó tí wọn ń kó sápò - Ìjọba Ọyọ
- Kìí ṣe torí gbígba àmì ẹ̀yẹ ni ọmọ wa ṣe kú, a dúpẹ́ lọ́wọ́ ìjọba tẹ rántí rẹ̀ - Ẹbí Adadevoh
- Ibà Lassa wọ ìpínlẹ̀ Èkó!
Akẹkọ naa la gbọ pe o gba maaki okoolerugba o din mẹsan ninu idanwo asewọle sile ẹkọ naa , to si fẹ kọ nipa isẹ ibaraẹnisọrọ, Mass Communication.
Amọ riro ni ti eniyan, sise ni ti Ọlọrun, lẹyin ti ọmọ yii kuna lati ni maaki tileẹkọ naa n beere fun lori imọ isẹ to fẹ se, ni baba ọmọdebinrin naa ba tọ Baruwa lọ.

Oríṣun àwòrán, Others
Baruwa, to n fi isẹ olukọ se idabọ ni ẹka imọ nipa isiro owo lo si gba lati seranwọ fun baba naa, to si gbe ọmọ ọhun ls sile ẹkọ fasiti naa lọjọ kẹtalelogun osu keje ọdun 2015.
Amọ ẹni ti a gboju okun le, ti ko jọ ẹni agba ni olukọ naa, tori o fi tipa ba ọmọdebinrin naa lopọ ni aago mẹsan kọja isẹju mẹẹdọgbọn aarọ ni yara kẹjọ to wa ni ọọfisi ẹkọ nipa isẹ okoowo.

Oríṣun àwòrán, Others
Ọmọbinrin naa ko fi isẹlẹ yii se osun, ko fi kinra, amọ o dele, o sọ fun awọn obi rẹ, ti ọrọ naa si de etigbọ ẹgbẹ ajafẹtọ ẹni kan, to gba ẹjọ ọhun kanri.
- Lekan Balogun, dá ₦6.5m owó oyè tó gbà lọ́wọ́ òkú padà, àwọn ará ilé rẹ̀ ń bèèrè - Olúbàdàn
- Oyè Ibadan kò sí fún títà - Otun Olubadan, Lekan Balogun
- Owó àwọn aṣòfin kò pọ̀jù, iṣẹ́ kàbàtì tí wọn ń ṣe ju owó oṣù wọn lọ - Buhari
- Kò síbi tó dàbí ilé, tìlù-tìfọn ni wọ́n fi kí Anthony Joshua tó bẹ ìlú rẹ̀, Ṣágámù wò káàbọ̀
- Àbòsí ló wà níbẹ̀ tí ìpínlẹ̀ Eko ò bá ṣe Amotekun- Bode George
Nigba to n gbe idajọ rẹ kalẹ lori ẹsun naa, Adajọ Josephine Oyefẹsọ ni afurasi naa mọ bi ọran to da se lowura to, ati bi ijiya rẹ se gbopọn si, nitori oun lo fi tipa jabale ọmọ naa.
O ni ọgbẹ ọkan nla ti yoo wa titi aye ni isẹlẹ naa jẹ fun ọmọbinrin ọhun, eyi toun n gbadura pe ko san.
Lẹyin eyi lo wa ni ko lọ fi asọ penpe roko ọba fun ọdun mọkanlelogun gbako.













