Covid-19: Wo àwọn kìnìún tó kó covid-19 lára àwọn èèyàn

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Iṣeniyan ṣe ẹranko, ṣebi awọn eeyan lo n paya pe ki wọn maa lugbadi arun covid-19 to n ṣọṣẹ kaakiri agbaye.
Ewo tun wa ni tawọn ẹranko kan bayii ti iroyin sọ pe o ṣeeṣe ki wọn ti karun coronavirus.
Awọn onimọ sayẹnsi fasiti Pretoria lo sọ pe o ṣeeṣe kawọn olutọju ọgba ẹranko ẹranko lorilẹede South Africa ti ko arun covid-19 ran awọn kiniun kan lọgba ẹranko.
- Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ mánigbàgbé tó wáyé lọdún 2021
- Ṣé lóòtọ́ ni gómìnà ìpínlẹ̀ Abia àti Imo wọ àṣo àsíí Biafra bí o ṣe jáde lórí ayélujára?
- Ọlọ́run Tinubu kìí ṣé Ọlọ́run témi torínáà mi o ní gbè lẹyìn rẹ̀ ní 2023- Ojudu
- Ilé ẹjọ́ gbà béèlì ìgba mílíọ̀nù Naira(N200m) lórí ẹsùn tí EFCC fi kàn Mompha
- Wo Mẹkáníìkì alápá kan tí ayé ń pariwo pé o mọ ìjánu ọkọ̀ ṣe púpọ̀
- Wo Mẹkáníìkì alápá kan tí ayé ń pariwo pé o mọ ìjánu ọkọ̀ ṣe púpọ̀
Awọn onimọ ijinlẹ sayẹnsi ọhun n kọminu iru ẹda covid-19 to le jẹyọ tawọn eeyan ba ko covid-19 lara awọn ẹranko yii.
Awọn onimọ ijinlẹ ṣe ayẹwo awọn ẹranko naa lẹyin ti wọn ṣe akiyesi apẹẹrẹ arun covid-19 lara awọn kiniun yii.
Wọn ri pe awọn kiniun yii ko le mi daadaa, wọn si tun n ṣe ikun, bakan naa ni wọn n wukọ.
Awọn onimọ sayẹnsi naa sọ pe esi ayẹwo ọhun fihan pe lara awọn to n tọju awọn ẹranko ọhun ni wọn ti ko covid-19.
Wọn ni ọpọ ninu awọn olutọju awọn ẹranko ọhun ni wọn ni arun covid-19 lasiko naa ṣugbọn wọn ko fi apẹẹrẹ han.
Awọn onimọ sayẹnsi naa wa rọ awọn olutọju ẹranko lati maa wọ ibomu ti wọn ba ti n tọju awọn ẹranko.












