Amotekun: Miyetti Allah ní òun yóò péjú síbi ìpàdé ìta gbangba lọ́jọ́ Ajé láti sọ tẹnu òun

Bi wọn ba n ke gbe gbe gbe, ti a ko ba bawọn gbe, afaimọ ki wọn ma gbe si ẹyinkule wa.
Idi ree ti ẹgbẹ Miyetti Allah to jẹ awọn olusin maalu lorilẹede Naijiria, ti wọn jẹ ẹya Fulani, naa fi n kede faraye pe awọn ko ni gbẹyin nibi ipade ita gbangba lori agbekalẹ ẹsẹ alaabo Amotekun ti yoo waye lọjọ Aje.
- Amotekun: Kí ni iṣẹ́ tí Amotekun yóò máa ṣe gangan?
- Irọ̀ ni ìjọba ń pa, Ikọ Amọtẹkun ba ofin Naijiria mu- Ìgbìmọ̀ Yoruba
- Tinubu kò ṣékú, kò ṣé ẹyẹ, o n dibọn ní lórí ọ̀rọ̀ ikọ̀ Amotekun - Fani Kayode
- Digbí ni mo wà lẹ́yìn Amotekun, máà ṣèrànwọ́ mílíọ̀nú èèyàn fun - Nnamdi Kanu
- Ẹ̀bùn ọdún tuntun tó yááyì ni ikọ̀ Amotekun - Soyinka
- Ìbẹ̀rù nípa Amotekun ló ń mú káwọn èèyàn kan máa wí ìwíkùwí - Soyinka
Miyetti Allah ni awọn fẹ lọ sibi ipade ita gbangba ọhun lati fi ero awọn han lori ifilọlẹ ikọ alaabo ọhun lẹkun iwọ oorun guusu Naijiria.

Oríṣun àwòrán, @tosinsammy_s
Alaga ẹgbẹ Miyetti Allah nipinlẹ Ogun, Abdulmumin Ibrahim sọ fawọn akọroyin pe ko yẹ ko jẹ ẹya Yoruba nikan ni yoo wa ninu ẹsẹ alaabo Amotẹkun niwọn igba ti yoo dojukọ aawọ to maa n waye laarin awọn agbẹ ati darandaran.
Ibrahim ni awọn ko fẹ ki wọn sọ ẹsọ alaabo Amotekun di ẹgbẹ ọmọbibi ilẹ Oodua, OPC, o si yẹ ki wọn gba awọn ọmọ ẹgbẹ Miyetti Allah sinu ikọ Amọtẹkun naa, ko lee fidi mulẹ bo se yẹ.

Ko tan sibẹ, akẹẹgbẹ rẹ lati ipinlẹ Ondo, Alhaji Garuba Bello naa ni awọn ọmọ ẹgbẹ Miyetti Allah yoo bawọn peju sibi ipade gbangba lori Amotekun lọjọ Aje, to si fikun pe oun tijọba ba ni ki awọn se, lawọn yoo se.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Buhari, kí ló dé tó fẹ́ dá $100m owó Abacha padà fún gómìnà Kebbi? - Amẹ́ríkà fọnmú
- Èmi àti Kolington kò fẹ́ra padà o, ọba Wákà kò fẹ́ ọba Fuji mọ́ - Salawa Abeni
- Èmi sì ní Oluwo tilẹ̀ Iwo, kò sí ìgbìmọ̀ ọba kankan tó lè ní kí ń rọ́ọ́kún nílé - Oluwo
- Toyin Abraham ọkọ rẹ̀ àti Ire ní London, Odunlade 'kòlábò' pẹ̀lú Mercy Aigbe
- Èlé owó iná ọba kọ́ ló kàn, ẹ kọ́ ṣàtúnṣe sí ìlànà àdánú tẹ́ ń ṣe fún wa - Iléeṣẹ́ apínná sọ fún ìjọba
Bẹẹ ba si gbagbe, ẹgbẹ Miyetti Allah yi lo ti n tako agbekalẹ eto alaabo Amotekun latẹyinwa, ti wọn si ni afojusun eto naa ni lati le ẹya Fulani jinna rere si ẹkun iwọ oorun guusu Naijiria.
Amọ awọn gomina to wa nilẹ Yoruba ti wa sọ fawọn Fulani pe ibẹru wọn yii ko lẹsẹ nilẹ, ko si tọ, bẹẹ ni ko pọn dandan.













