Minimum Wage: NLC ní àfikún owó oṣù nìkan lẹ̀rọ̀ ìyanṣẹ́lódì

Oríṣun àwòrán, @NLCHQ_ABUJA
Ẹgbẹ oṣiṣẹ lorilẹede Naijiria, NLC, ti sọ fun awọn adari ẹgbẹ ọhun lawọn ipinlẹ pe ki wọn gbaradi fun iyanṣẹlodi, bẹrẹ lati lọjọru, ọjọ Kẹrindinlogun oṣu Kẹwa ọdun 2019.
Ẹgbẹ NLC ni oun yoo gunle iyaṣẹlodi naa ti ifọrọwerọ oun pẹlu ijọba apapọ ko ba so eso rere.
Ninu atẹjade kan ti ẹgbẹ naa fi sọwọ si awọn ẹka rẹ ni awọn ipinlẹ, ti akọwe agba ẹgbẹ, Emmanuel Ugboaja fọwọ si, l oti sisọ loju ọrọ naa.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- "Ọmọ ọdún méje ni mo bẹ̀rẹ̀ òwò nàbì nílé aṣẹ́wó tó tóbi jùlọ lágbàyéé"
- Ẹ jọ̀ọ́, òógùn ojú mi kò gbọdọ̀ já sásán lórí sinimá tí mo yà pẹ̀lú oyún oṣù mẹ́fà - Toyin Abraham
- Kí ni àyájọ́ ‘Má wọ kọ́mú’ wà fún?
- Kò sí òògùn kankan tó ń mú mi bí ìbejì bíkòṣe oúnjẹ ìbílẹ̀ - Aláàfin Ọyọ
- Àwòrán bí ẹ̀kún omi ti ṣọṣé l'Eko àtàwọn ìlú míì nílẹ̀ Yorùbá rèé
Ẹgbẹ NLC ni, gẹgẹ bi iwe ti oun ti kọ ṣaaju si awọn ọmọ ẹgbẹ naa ni Naijiria pe, ti ajọsọ egbẹ naa pẹlu ijọba apapọ lori afikun owo oṣu ko ba so eso rere, oun yoo bẹrẹ iyanṣẹlodi.

Oríṣun àwòrán, @NLCHQ_ABUJA
Ṣaaju ni ẹgbẹ awọn oṣiṣẹ ọhun ti beere afikun owo oṣu to jẹ ida mọkanla fun awọn oṣiṣẹ to wa ni ipele keje si mẹrinla, ati afikun owo oṣu ida mẹfa abọ fun awọn oṣiṣẹ ijọba to wa ni ipele karundilogun titi de ipele kẹtadinlogun.
Ni ọjọ kẹrinla oṣu karun un ọdun 2019 ni ijọba apapọ gbe igbimọ kan dide lati boju wo afikun ti ẹgbẹ oṣiṣẹ n beere fun.
- Odunlade fijó bẹ́ẹ, Lizzy padà sọ́dún 2012, Toyin Abraham tọ̀ lẹ́ẹ̀mẹwàá
- Àwòrán bí ẹ̀kún omi ti ṣọṣé l'Eko àtàwọn ìlú míì nílẹ̀ Yorùbá rèé
- Ṣé ìpèsè iná ọba yóò wà lọ̀dún 2020 torí ₦9bn nìjọba fẹ́ ná fún ẹ̀rọ amúnáwá?
- Ẹ jọ̀ọ́, òógùn ojú mi kò gbọdọ̀ já sásán lórí sinimá tí mo yà pẹ̀lú oyún oṣù mẹ́fà - Toyin Abraham
- Kò sí òògùn kankan tó ń mú mi bí ìbejì bíkòṣe oúnjẹ ìbílẹ̀ - Aláàfin Ọyọ
Lẹyin ọpọlọpọ ipade ati ijiroro, o jọ pe ẹ́gbẹ oṣiṣẹ ati ijọba apapọ ko tii fẹnu ọrọ naa jona.








