Fayoṣe: Gómìnà Fayemi kò nílò ẹjọ́, torí àti ṣe ohun ti ìjọba àná kò leè ṣe ní wọ́n fi dìbò fún un

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Gomina Fayẹmi ti ipinlẹ Ekiti ti fi ẹsun kan iṣejọba ana ni ipinlẹ naa labẹ Ayọdele Fayose pe biliọnu mẹtadinlọgọta lo jẹ awọn oṣiṣẹ gẹgẹ bii owo oṣu ati ajẹmọnu gbogbo.
Amọṣa, Fayoṣe pẹlu ti da esi pada pe, ariwo lasan ni Fayẹmi n pa ati pe iṣẹ ni awọn eeyan ipinlẹ Ekiti yan an lati wa ṣe kii ṣe ariwo.
- Mr Latin, Jide Kosọkọ àti Mama Rainbow sọ̀rọ̀ lórí ìjà Toyin ati Lizzy
- ‘A ó gbé ìdílé Kayọde Fayẹmi ṣépè tí àwọn akẹ́kọ́ tó ṣèṣe bá kú!’
- Gómìnà ìpínlẹ Kwara yan Kọmíṣónnà tí ó kéré julọ!
- Oògùn olóró cocaine ni Toyin Abraham fi ń sayé - Lizzy Anjorin
- Èèyàn mẹ́ta kú nígbà tí ọkọ̀ bọ́ọ̀sì jábọ́ sí ódò Ọ̀ṣun
- Fayemi dá iléèwé Christ School padà fún ìjọ Anglican
Nibi ipade kan pẹlu awọn oṣiṣẹ ijọba nilu Ado Ekiti ni gomina Fayẹmi ti kede ọrọ naa. O ni iṣejọba oun n sa ipa gbogbo to yẹ lati san awọn ajẹẹlẹ owo oṣu ati ajẹmọnu naa.
O ni segesege lori ilana sisan owo oṣu naa lo ṣokunfa bi o ti ṣe wa di oke nla niwaju ijọba bayii.
Fayẹmi ni ajẹsilẹ owo oṣu naa wa laarin ọdun 2014 si oṣu kẹwa ọdun 2018.
Nigba ti o n dahun loju opo twitter rẹ, Gomina ana, Ayọdele Fayoṣe ni iyalẹnu ni ọrọ ti Fayẹmi sọ jẹ fun oun ṣugbọn o ni oun "rọ ọ lati san owo oṣu oṣiṣẹ nitori eredi ti araalu fi dibo yan an ni lati ṣe oun ti oun ko lee ṣe"
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post








