Jollof rice: Ṣé lóòtọ́ ni ìrẹsì jọ̀lọ́ọ̀fù Ghana dùn ju ìrẹsì jọ̀lọ́ọ̀fù Nàìjíríà lọ?

Oríṣun àwòrán, @EarlJoey_.
Kii ṣe ana ni ariyanjiyan laarin awọn eeyan, paapaa julọ, awọn ọmọ orilẹede Naijiria ati Ghana ti n waye lori irẹsi jọlọọfu ẹni to dun julọ ninu ti orilẹede mejeeji.
Amọṣa, ariyanjiyan naa n dabi eyi ti wọn ti wa ojutu si bayii lẹyin ti alase ọmọ ọdun mẹrinlelogun kan lati orilẹede Ghana, Sika Mortoo, fi ajulọ han akẹgbẹ rẹ lati orilẹede Naijiria, nibi idije ase kan to waye.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Àwọn ọmọ Nàíjíríà ló ṣiṣẹ́ takò mí ní Ireland kí ń má baà wọlé ìbò Káńsélọ̀ - Yemi Adenuga
- Láti January lọ, gbogbo ẹni tó bá ra ọjà lórí ayélujára yóò máa sanwó orí - FIRS
- Owó dé! ₦30,000 owó oṣù yòó bẹ̀rẹ̀ ní September - Alága ẹgbẹ́ òṣìṣẹ́ l‘Ekiti
- Ìyá tó lu ọmọ ọdún mẹ́rin pa l‘Akurẹ bọ́ sọ́wọ́ ọlọ́pàá
- Bíodun Fatoyinbo ti fojú hàn ní àgọ ọlọpàá
Idije Onga Jollof Battle to waye lopin ọsẹ to kọja nilu Accra laarin awọn alase meji naa lati mọ orilẹ€de ti irẹsi jọlọọfu rẹ dun julọ.
Gbajugbaja ounjẹ, ari ma lee lọ ni irẹsi jọlọọfu ni ẹkun iwọ oorun Afirika eyi ti wọn maa n fi irẹsi, tomato atawọn eroja miran ṣe.

Oríṣun àwòrán, PrOMAISODOR GHANA
Ilumọọka ni irẹsi jọlọọfu laarin awọn ọmọ orilẹede bii Senegal, Ghana, Naijiria, Gambia, Sierra Leone, Liberia ati cameroon.
Fun ọdun diẹ sẹyin bayii ni ariyanjiyan ti n waye laarin awọn ọmọ Naijiria ati Ghana lori ikoko irẹsi jọlọọfu to ṣee jẹ ni ajẹpọnula julọ laarin orilẹede mejeeji.

Oríṣun àwòrán, PrOMAISODOR GHANA
Lẹyin ti awọn adajọ ṣe itọwo abọ irẹsi jọlọọfu ti wọn gbe wa, awọn mẹtẹẹta lo panupọ ṣalaye pe irẹsi jọlọọfu ti ghana lọba.
Orilẹede Ghana, Naijiria ati South Africa ni awọn adajs nibi idije naa ti wa.
- Aṣojú Seyí Makinde lásan ní mo jẹ, òṣìṣẹ́ gbọdọ̀ bọ̀wọ̀ fún mi - Ọ̀dọ́mọdé Kọmísánà
- Èmi àti Bọla Tinubu fẹ́ lo ‘German Mercenaries’ láti gbé MKO Abiọla kúrò lẹ́wọ̀n - Dele Momodu
- Irọ́ ńlá! Ẹgbẹ́ IPOB ò tako Ààrẹ Buhari ní Japan- Iléeṣẹ́ Ààrẹ
- Òfin nìkan ló lè gbadé lórí àwa Ọba ìlú lbadan- Oba Lekan Balogun
- Irọ́ ló pa, a kò mọ̀ ọ́ rí tàbí fún ọ ní ₦13m - APC tako afurasí ajínigbé
Sika Mortoo to gbe igba oroke nibi idije ase naa gba ẹbun owo ẹgbẹrun meji dọla ($2000), ọmọ Naijiria to baa dije, Chef Turay, naa si gba Ẹgbẹrun kan dọla ($1000).












