Adebayo Shittu: Ìyàlẹ́nu ló jẹ́ pé ń kò jẹ mínísítà lẹ́ẹ̀kejì

Ṣaaju eto idibo abẹle ẹgbẹ naa ni aṣiri tu pe Shittu ko kopa ninu eto isinru ilu (NYSC).

Oríṣun àwòrán, @HMAdebayoShittu

Minisita tẹlẹri feto ibaraẹnisọrọ ni Naijiria, Adebayo Shittu ti ṣe'mọ bi aarẹ Buhari ko ṣe yan sipo Minisita.

Ọgbẹni Shittu to fi ọrọ yii lede ninu ifọrọwanilẹnuwo pẹlu ile iṣẹ akoroyinjọ ilẹ wa, NANS, nilu Abuja wa fikun pe, oun ti gba ọrọ naa gẹgẹ bi akọọlẹ Ọlọrun nilana ẹsin musulumi.

Ninu orukọ awọn minisita tuntun ti Buhari yan sipo, eeyan mẹrinla to ti ṣiṣẹ tẹlẹ bii minisitani saa akọkọ, lorukọ wọn wa ninu rẹ, amọ ti orukọ Shittu ko si lara wọn.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Bakanna la ri minisita obinrin meje, ninu awọn mejidinlogun to jẹ minisita tẹlẹri kuna lati ri ipo bi ti Shittu.

''Lootọ ni pe mo fi ọkan si pe wọn yoo yan mi sipo pada ṣugbọn nigba ti ọrọ ko ri bẹẹ, ko gba mi ni iṣẹju marun un lati gba wi pe akọsilẹ ni ati pe bi Ọlọrun ti ṣe fẹ ẹ ni yẹn''

O fi kun ọrọ rẹ pe ''Mo si ti ri ohun to tu mi ninu latara ẹsẹ Kurani, nibi ti Ọlọrun ti ṣe adehun pe oun to n bọ lọna, lati fun ọ ni ohun to dara ju eleyi to wa lọwọ rẹ bayi lọ''

Adebayo Shittu

Oríṣun àwòrán, @HMAdebayoShittu

Nigba to n sọrọ lori ohun ti yoo wa maa ṣe bayii lẹyin to kuna lati dipo minisita mu, ọgbẹni Shittu sọ pe oun yoo pada si idi iṣẹ amofin eleyi toun ti n ṣe saaju oṣelu.

Bi a ko ba gbagbe, ọmọ bibi ipinlẹ Oyo naa kuna lati ri tikẹẹti gba, eyi ti yoo fun laanfaani lati ṣoju ẹgbẹ APC ninu idibo Gomina to kọja nipinlẹ Oyo.

Idi ni pe ẹgbẹ APC ja Shittu kulẹ tori pe ko kopa ninu eto agunbanirọ ọlọdun kan, eleyi ti a mọ si NYSC.