Wọle Ṣoyinka: Ẹ máṣe gba gbogbo ohun tẹ bá rí lórí ayélujára gbọ́ nípa mi

Ọjọgbọn Wole Soyinka

Oríṣun àwòrán, @akhirebhulu

Ọjọgbọn Wọle Ṣoyinka ti sọ fun ijọba apapọ pe ko ye fi awọn oṣiṣẹ eleto aabo dunkoko mọ awọn Naijiria mọ.

Ọjọgbọn Ṣoyinka ni iwa ki awọn agbofinro ma halẹ mọ awọn eeyan nibi ti wọn ba ti n takurọsọ, ku diẹ kaato.

Ṣoyinka sọrọ yii niluu Badagry nibi to ti lọ ṣi iṣẹ ọna kan to nii ṣe pẹlu ayajọ ọjọ ibi rẹ.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Ọjọgbọn Ṣoyinka sọ pe, nigba ku gba ti ijọba ba n fi awọn ologun, ọlọpaa atawọn ọtẹlẹmuyẹ dunkoko mọ ara ilu, o tumọ si pe ijọba n bẹru ni.

O fi kun ọrọ rẹ pe, iru igbesẹ bẹẹ maa n ṣe adinku eeyan gẹgẹ bi ẹlẹran ara nitori o fihan pe, ijọba ko fẹ gbọ ohun ti ara ilu n wi ni.

Bẹẹ ba gbagbe, lọjọ Aje ọsẹ to lọ ni Ikeja niluu Eko lawọn ologun, ọlọpaa ati ọtẹlẹmuyẹ ti gbọngan kan pa, eyi tawọn ajafẹtọ ọmọniyan bii Ṣoyinka, agbẹjọro Femi Falana atawọn eeyan miran, ti fẹ ṣe apero.

Ọjọgbọn Wole Soyinka

Oríṣun àwòrán, @akhirebhulu

Ṣọyinka wa rọ ijọba atawọn oṣiṣẹ eleto aabo lati jawọ ninu apọn ti o yọ, ki wọn da omi ila kana.

Ọjọgbọn Ṣoyinka tun rọ awọn ọmọ Naijiria pe, ki wọn mase gba gbogbo iroyin ti wọn ri lori ayelujara gbọ.

O ṣalaye pe, ewu to wa ninu iroyin ori ayelujara pọ nitori ni iṣẹju akan ni yoo tan kalẹ kaakiri.

Ṣoyinka ni ọpọ igba lawọn eeyan maa n lo orukọ ati fọto oun fun iroyin lori ayelujara, nigba t'oun o tiẹ sọrọ kankan.