Funke Dosumu on World TB Day: N kò rí ọmọ mi fún ọdún kan torí ikọ́ fée ti mo ní"
"Mi ò lè sùn, jẹun, mò ǹ wúkọ́ ní gbogbo oru, mò ń làágùn..."
Oni yii, tii se ọjọ́ Kẹrìnlélógún oṣù Kẹta ni ajọ isọkan agbaye ya sọtọ gẹgẹ bii ayajọ lati gbogun ti arun ikọ ife.
Idi ree ti BBC Yoruba fi tọ obinrin kan, Funkẹ Dosumu lọ, ẹni to ti ni arun yi ri, amọ́ ti ori ko yọ.
Nigba to n salaye ohun ti oju rẹ ri, Funkẹ ni ohun to dun oun julọ lasiko ti oun wa lori akete arun naa ni pe, oun ko fi oju ri ọmọ oun tii se ọmọ ọdun kan.
- Ilé ẹjọ́ pàṣẹ́ fún ìyá tó lu olùkọ́ ọmọ rẹ ní Ogun láti gbá ọgbà ilé ẹ̀kọ́ nàá fún oṣù mẹ́fà
- Mọ̀ nípa ìlànà tí wọ́n n gbà yan ọ̀gá àgbà Fásítì, VC ní Naijiria
- Gómìnà Oyetola rawọ́ ẹ̀bẹ̀ sáwọn aráàlù atí Oníṣẹ̀ṣe tó fẹ̀hónúhàn ní OAU torí VC tuntun tí kìí ṣe ọmọ ìlú
- 'Ọjọ́ méjì àti wákàtí díẹ̀ péré la fún Ramon Adedoyin láti gbé ìwée 'a kò ní ẹjọ́ jẹ́' wá sílé ẹjọ́'
O fikun pe, se ni wọn ya oun sọtọ ninu yara kan, lai darapọ mọ ọkọ, ọmọ ati gbogbo ẹbi rẹ lapapọ.
Obinrin naa tẹ siwaju pe, lara apẹẹrẹ ti oun n ri pe oun ni arun ikọ ife ni pe oun n wukọ lemọlemọ, oun kii sun loru tori ikọ wiwu, oun n laagun pupọ, ounjẹ kii wu oun jẹ, ti oun si n ru.
- Kíni ìwọ mọ̀ nípa Funmilayọ Ransome-Kuti?
- Ẹfunsetan Aniwura, obìnrin tó ju ọkùnrin lọ
- Hubert Ogunde rèé, baba àwọn òsèré tíátà
- Kí lo fẹ́ mọ̀ nípa ‘Ajala Travels’?
- Wòlíì Kasali ní Dolapo Awosika kò lé ìyàwó òun jáde
- 'Alífábẹ́ẹ́tì Ohùn Oduduwa di ìtẹ́wọ́gbà ni Ajaṣẹ'
- Ṣẹ gbọ́ nípa Alájọ Ṣómólú, tó ta mọ́tò ra kẹ̀kẹ́?
- Oshisko twins, àwọn 'ìbejì' tó ń dẹ́rìn ín p'òṣónú
Funkẹ to ye arun ikọ ife la, wa rawọ ẹbẹ sawọn eeyan to ba ti n wukọ lemọlemọ, lati lọ se ayẹwo nile iwosan, tori o lee jẹ arun ikọ ife.
Bakan naa, lo tun rọ awọn eeyan to ni arun ikọ ife lati maa lọ fun itọju deede, ki wọn maa lo oogun ati abẹrẹ wọn bo ti yẹ, ki iwosan lee tete de bawọn, tori ikọ ife kii pa ẹni to ba tọju ara rẹ.