Timothy Adegoke death case: Àwọn ẹbí Rahmon Adedoyin àti Timothy Adegoke ju òkò ọ̀rọ̀ lu ara wọn nílé ẹjọ́

Oríṣun àwòrán, Others
Ìgbẹ́jọ́ lórí ohun tó sọkùnfà ikú Timothy Adegoke, akẹ́kọ̀ọ́ oyè ìmọ̀ kejì ní ilé ẹ̀kọ́ gíga fásitì Obafemi Awolowo, Ile Ife, ìpínlẹ̀ Osun tó kú sí ilé ìtura Hilton ti bẹ̀rẹ̀ .
Ẹ ó rántí pé àjọ ọlọ́pàá ti wọ́ ẹni tó ni ilé ìtura Hilton náà, Dókítà Ramon Adedoyin àti àwọn mẹ́fà mìíràn lọ sí ilé ẹjọ́ gíga kan nílùú Abuja lórí ikú Timothy Adegoke tó kú sí ilé ìtura náà lọ́jọ́ kẹfà, oṣù kọkànlá, ọdún 2021.
- Musulumi àti Kristẹni lo ṣe àdúrà níbi ètò ìsìnkú Timothy Adegoke lónìí
- Ǹkan tí mo fẹ́ ni kí wọ́n sunkún nílé àwọn tó pa abúrò mi náà torí wọ́n pa wá lẹ́kún - Ẹ̀gbọ́n Timothy Adegoke
- Ẹ̀jọ́ àtí ìwádìí ikú Timothy Adegoke ti kúró lọ́dọ̀ọ wa nípinlẹ̀ Osun- Agbẹnusọ Ọlọ́pàá Oṣun
- Ramon Adedoyin t'ọ́lọ́pàá mú nítorí ikú Timothy Adegoke gba ilé ẹjọ́ lọ, ohun tílé ẹjọ́ sọ rèé...
- A kò fi ẹbí Timothy sílẹ̀, à ń gbiyànjú pé kí wọ́n dá ẹjọ́ náà padà sí Osun dípò Abuja ni- Agbẹjọ́rò Adekilekun
- Ṣé lóòtọ́ ni ọlọ́pàá Osun fẹ́ fi panpẹ́ mú ọmọ Adedoyin tó ni Hòtẹ́ẹ̀lì tí Timothy Adegoke kú sí? Ọ̀rọ̀ ń rùn bọ̀ o
- Timothy Adegoke yóò wọ ilẹ̀ sùn lọ́jọ́ Àbámẹ́ta, bí ìsìnkú rẹ̀ yóò ṣe lọ rèé
Lára ẹ̀sùn tí wọ́n fi kàn Adedoyin ni sínsin òkú Adegoke lọ́nà àìtọ́, pípa ẹ̀rí ìwé owó tí Timothy Adegoke fi san owó rẹ́ àti yíyọ ẹ̀rọ ayàwòrán (CCTV) ilé ìtura náà rẹ́ lójúnà àti pa àwọn ohun tí kò bá jẹ́ ohun ẹ̀rí rẹ́.
Ẹ̀sùn ìpànìyàn, ìlẹ̀dí-àpòpọ̀, àti àwọn ẹ̀sùn mìíràn ni wọ́n fi kan àwọn mẹ́fà tó kù.
Ki lo ṣẹlẹ lọjọ Ru?
Lẹ́yìn ìgbẹ́jọ́ ilé ẹjọ́ ní ọjọ́'Rú, Fọ́nrán kan ṣe àfihàn ibi tí àwọn mọ̀lẹ́bí méjéèjì tí ń sọ òkò ọ̀rs lu ara wọn.
Àwọn ẹbí méjéèjì ń bú ara wọn pé wọ́n yóò kú.
Bẹẹ naa ni wọn n leri pẹlu itara si ara wọn















