Ayelala Idol: Onímọlẹ̀ ní olúwẹri obìnrin ni òrìṣà náà ló ṣe ń pọn omi sínú ẹlẹ́ṣẹ̀
Eeyan to ba ni awọn ara ijọun gọ, o ti bu baba nla rẹ mọ.
Ni igba atijọ, oniruuru ọna ni Yoruba n gba se akoso ilu, lati jẹ ki iwa ọdaran dinku, ti wọn si n se idajọ ara wọn.
Lara ilana fun afọmọ ilu naa ni amulo awọn orisa ilẹ Yoruba fun idajọ ẹlẹsẹ, inu wọn si ni orisa Ayelala wa.
Orisa yii si lo maa n se idajọ oju ẹsẹ fun awọn eeyan to ba huwa ibajẹ lawujọ lai segbe si ẹyin ẹlẹsẹ kankan.
Ọna lati mọ nipa orisa onidajọ oju ẹsẹ yii lo gbe BBC Yoruba lọ silu Okiti Pupa nibi ti ojubọ orisa Ayelala ti rinlẹ.
- Ṣé o mọ àwọn òrìṣà ìṣẹ̀mbáyé méje tó di ilẹ̀ gbogbo àgbáyé mú?
- Ìgunnukó nìyí, òrìsà Tápà, òrìsà olówó àti tọlọ́mọ
- Adunni Olorisa, obìnrin òyìnbó tó di ìyàwó òrìṣà nílẹ̀ Yorùbá títí di ọjọ́ ogbó
- Fídíò rèé nípa bí Aláké tuntun ṣe ń gba ìwúre lábẹ́ Olúmọ kó tó gba adé
- Àwọn alálẹ̀ kò ní forí jìn mí tí ń kò bá ṣe ọdún Ṣàngó - Alaafin
- Wo èèwọ̀ tó so mọ́ ọdún Ẹ̀yọ̀, tí obìnrin kìí fií di Sùkú tàbí wé gèlè
Nigba to n ba BBC Yoruba sọrọ, Onimọlẹ Ayelala, Oloye Araye Holo salaye ọna ti Ayelala maa n gba mu ọdaran ati oniruuru iya to fi n jẹ wọn.
Holo ni Oluwẹri obinrin ni orisa Ayelala, idi si ree to se maa n pọn omi sinu ẹlẹsẹ.
O fikun pe awọn ẹlẹsin maa n tako orisa naa loju aye amọ wọn maa n gba ẹyin wa sọdọ rẹ fun iranlọwọ.
Àwọn ìtàn mánigbàgbé tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Hubert Ogunde rèé, baba àwọn òsèré tíátà
- Kí lo fẹ́ mọ̀ nípa ‘Ajala Travels’?
- Ṣẹ gbọ́ nípa Alájọ Ṣómólú, tó ta mọ́tò ra kẹ̀kẹ́?
- Ẹfunroye Tinubu - Ògbóǹtagí oníṣòwò, olówò ẹrú àti afọbajẹ
- Samuel Ajayi Crowther, òjíṣẹ́ Ọlọ́run tó gbé èdè Yoruba lárugẹ
- Mọrèmi Àjàṣorò, akọni obìnrin tó gba Ilé Ifẹ̀ sílẹ̀ lóko ẹrú
- Ọ̀rọ̀ǹpọ̀tọ̀niyùn, Aláàfin obìnrin àkọ́kọ́ rèé, tó ní nǹkan ọkùnrin
- Baṣọ̀run Gáà, tó yan ọba mẹ́rin, pa ọba mẹ́rin àmọ́ ọba karùn-ún ló pa á
Bakan naa ni awọn eeyan kan tun jẹri si bi agbara orisa Ayelala ti pọ to atawọn sna to maa n gba se idajọ ẹlẹsẹ laisegbe sibikan.





