2021 Prophecies: Àwọn Mùsùlùmí náà ṣe àdúrà ọ̀dún túntún tó wolé dé wẹ́rẹ́

Àkọlé fídíò, Ọpọlọpọ Alfa ati pasitọ lo n fi adura ọdun ranṣẹ ati awọn afojusun to fi mọ asọtẹlẹ.

Shelkh Yahyah Olorunosebi Oshoala to jẹ Imam Agba Mosalasi Oriwu Central Mosque ti fi adura nla nla ranṣẹ si awọn ọmọ Naijiria ninu ọdun tuntun.

Imam gbadura wi pe ki Olorun ma jẹ ki a ri gbogbo ibanujẹ to ṣẹlẹ ni ọdun 2020 mọ ninu ọdun tuntun yii.

Bakan naa ni Imam gbadura pe ki opin de si imọtaraẹni nikan ati gbogbo iwa ajẹbanu lorilẹede Naijiria.