#BBCOGUNDEBATE: Ìjọba mi yóo dé gbogbo ẹsẹ̀kùkú àti ìgbèríko -Akinlade

Awon Oludije
Àkọlé àwòrán, #BBCOGUNDEBATE: O ṣe pataki láti yan àwọn akanda ẹda si ipò kọmisọna.
Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 6

Nínú ọ̀rọ̀ ìkádìí wọn, Ogunbanjọ ní òun ni ọmọde to wa laaarin won. Ọmọde si ni a n ran nisẹ.

Ó rọ gbogbo awọn oludije to ku àti awon eeyan ipinle ogun kí wọn ran oun nise. O ni oun ko lee dáa ṣe lai si iranwọ araalu. O ni ki won ma ta ibo wọn. O ni bi won ba gbe owo wa ki won gba a nitori won n fi owo abu se abu lalejo ni.

Akinlade ni bi oun ba di gomina, gbogbo nnkan ti oun ti ko ninu oṣelu ni oun yoo lo lati rii pe ipinle ogun lo siwaju. O ni ijoba oun yoo lo de gbogbo esekuku ati igberiko oun ko si ni ye kuro lori oun ti oun so.

awon ara ilu
Àkọlé àwòrán, #BBCOGUNDEBATE: Ijọba mi yoo de gbogbo ẹsẹkuku ati igberiko -Akinlade

GNI ní ti rẹ̀ sọ̀rọ̀ ni ede ẹgba o si tun salaye pe oun yoo sejoba pelu ogbon imo oye ati ifokansin ati iberu Olorun

Paseda ni ki won o maa ran omode nise ki won ran paseda nise. O ni oun setan lati pa iṣẹ da ati lati pa ise awon Obayejẹ oloselu da.

#BBCOGUNDEBATE: O ṣe pataki láti yan àwọn akanda ẹda si ipò kọmisọna.

Awon ara ilú lásiko ti wọn gbọrọ lnu àwọn olùdíje
Àkọlé àwòrán, #BBCGOVDEBATE: Kò sí ètò ilera ọfk fun àwọn obinrin- Ogunbanjọ

Pasẹda ni eto ilera alabode ko si ni ipo to daara.

Isejoba oun yoo si lo awon agunbaniro atawon akeko to ni imo isegun lati maa sise lawon ile iwosan alabode

Gboyega Isiaka ní ti rẹ sàlaàyé pe àwọn ile iwosan alabọde ko dara to ní ti Health Insurance ǹkan to se pataki ni

Awọn ómọde gbọdọ ni ànfani si ètò ilera ọfẹ pàápàá jùlọ àwọn obinrin, àti àgbpalagbà.

Ademola Ogunbanjọ ní Inssuance o kìí ṣe ojuutu, ò ni ètò amuludun ló 'se pataki, kin àwọn oogun to wa nibẹ, àwọn osiṣẹ́ ǹkọ kíni àwọn ṣe mọ iṣẹ́ sí. Àwọn obinrin ò gbọdọ máà bèrè fun ètò ilera ọfẹ́ kí wọn tun maa bèrè fún ìdọgbágba nítori naa ilera ọfẹ yóò wà fun àwọn ọmọde àti àgbalagba nìkan.

Ogunbanjọ fi kún pé àwọn ọmọde àkanda ẹkọ ni ireti ['e kò si ibi ti àwọn kò le de. o ṣe pataki kí òun yan akanda ẹdá gẹ́gẹ́ bii kọmisọna.

Paṣeda ni tirẹ náà fi àra mọ ọ̀rọ̀ Ogunbanjọ lati yan kọmisọna àkànda ẹdá

Akinlade ni ijoba amosun ti fowo si iwe adojutofo ilera fun ipinle Ogun, isejoba oun yoo si tun tẹsiwaju lori re.

Isiaka ni eto ilera ko si ni ipo to joju. O ni akọkọ iṣẹ oun ni lati se koriya fawon oṣiṣẹ eto ilera. Ṣiṣi awon ileewosan alabode ti o wa ni titipa. O ni oun gbo nipa eto adojutofi ilera sugbọn oun ko tii ri nitorinaa oun yoo se ise lori re. O fi kun un pe eto ilera ofe fawon arugbo, ọmọ wẹwẹ, ati aboyun

Awon ara ilú lásiko ti wọn gbọrọ lnu àwọn olùdíje
Àkọlé àwòrán, #BBCOGUNDEBATE: O ṣe pataki láti yan àwọn akanda ẹda si ipò kọmisọna.
Ara ilu to n bere ibeere
Àkọlé àwòrán, #BBCOGUNDEBATE: O ṣe pataki láti yan àwọn akanda ẹda si ipò kọmisọna.

Ibeere lórí oro iná, ti wọn si dahun pe àwọn idọti ni àwọn a maa lo láti mú ina wá

Lori akanda eda, Akinlade ni oun yoo gbe ipin kan kale fun awon akanda lati gbadun awon eto ìjọba gbogbo.

Ogunbanjo, Akinlade, Gboyega, Paseda
Àkọlé àwòrán, #BBCGOVDEBATE: Ẹṣẹ Mẹ́ta ni ètò ìjọba fi lélẹ̀ ní Ogun

Ètò ti bẹ̀rẹ̀ ni pẹrẹwu báyìí ní ìpínlẹ̀ Ogun.

Ikanni BBC Yoruba ti lọ káàkiri àwọn ìpínlẹ̀ mẹ́rin ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ fún ìpàdé ìtagbagba yìí.

Ọ̀pọ̀ àwọn ará ìlú ló ti ń wọ tìkẹ́tìkẹ́ báyìí lọ si gbọ̀ngàn Olusegun Obasanjọ Libaray ní ìlú Abeokuta, ní bi tí wọn ó ti máá fí ojú ajé kan onisọ.

Ọ̀pọ̀ àwọn olùkópa wọnyìí ni wọn si tí ń sàlàyé ìdì ti wọn fi wá láti bẹ̀rẹ̀ ohun ti àwọn oludíje yìí fẹ́ ṣe fun ará ìlú, èyí ni wọn sàlàyé pé ti ó ba di ọjọ́ iwájú yóò fun àwọn láànfàní láti lé bi wọn lérèè ohun ti wọn sọ pé àwọn yóò ṣe.

Lati mọ bi ó ṣe ń lọ ẹ maa tẹ̀lé wa níbi

Skip Facebook post

Content is not available

View content on FacebookBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.

End of Facebook post

Ní bayìí àwọn olùdíje Demola Ogunbanjo ti ẹgbẹ́ òṣèlú ANN àti Adekunle Akinlade ti ẹgbẹ́ APM Gboyega Nasiru Isiaka ti ADC ti wa níkàlẹ̀ bayìí láti gbọ ǹbkan ti àwọn ará ìlú fẹ́ bi wọn.

Kókó ọ̀rọ̀ tí àwọn olùdíje kọ̀kọ̀ọ̀kan músọ

Adekunle Akinlade

Akinlade
Àkọlé àwòrán, #BBCOGUNDEBATE: Èrò àwọn oludije ṣe ọtọ̀ọ̀tọ lóri ètò ẹkọ Ofẹ

Lori Ile Ekọ TASUED: Ká kó àwọn ọmọ si ile iwe kọ ni pataki bíko ṣe kí ijọba gbéra sọ láti ṣee daradara, irinṣẹ igbalode ni yoo wa nibvẹ ki àwọn ọmọ ti yóò dangajia

Ẹto ẹkọ ọfẹ ṣe pataki ní ile ẹkọ alakọbẹre sugbọn ko lowo ninu lókè.

GNI
Àkọlé àwòrán, #BBCGOVDEBATE: Awọn àrá ipínlẹ̀ Ogun ti bẹ̀rẹ̀ ìjíròrò

GNI ní òun ni ẹmio òòtọ́ àti ẹmi ìfọkansìn, ọmọ ìmẹkọ Afọn ni wọn

Kosi ilé ẹkọ to yanranti

Ijọba to wa lóde ko ṣe ohun ti o tọ nítori naa ètò ẹkọ ofẹ ṣe pataki

Ademola Ogunbanjọ

Ogunbanjọ
Àkọlé àwòrán, #BBCGOVDEBATE: Èrò àwọn oludije ṣe ọtọ̀ọ̀tọ lóri ètò ẹkọ Ofẹ

Iberu olorun ni mo gbé dáni fún àwọn ènìyàn ìpínlẹ̀ Ogun

Lóri ètò Ẹto ẹkọ ò lé dara kó tun jẹ pọ́ọ́kú lówó, ó ṣe pàtàkí kí wọn san owọ

Gbogbo ǹkan to n fun wa ni wahala ni afe pada si. Itura ni wọn gbé wa fun àwọn eniyan ìpínlẹ̀ Ogun

Etò ẹkọ ọfe kò le ṣeeṣe bíkose se pe àtunto àwọn olùkọ gbọdọ jẹ koko.

Rotimi Paseda

Paseda
Àkọlé àwòrán, #BBCGOVDEBATE: Awọn àrá ipínlẹ̀ Ogun ti bẹ̀rẹ̀ ìjíròrò

Wọn ò fi ọgban ori gbé [pawọn ilé ìwé wa kalẹ, kò si sí ìdí ti wọn ó ṣe kó ilé [piwé si ojú kan

kò tọna láti maa ya owo ṣe ǹkan, dandan ni ètò ẹkọ ọfẹ́ ni ìpínlẹ̀ Ogun

Ilé iwe ẹkọ ní ọpọ̀ lọ kini ìdí ti à kò ṣe gbọdọ ṣe ní asìkò yìí. wọn jẹun tan wọn si fẹ ti ìl\lkun mọ àwọn tó kú. M aa ri daju pee gbogbo Yunifasiti ní yoo wa ni gbogbo ẹkun ipinlẹ Ogun ti mo ba di Gomina.

ÈTÒ ÀÀBÒ

Awon ara ilú lásiko ti wọn gbọrọ lnu àwọn olùdíje
Àkọlé àwòrán, Eto aabo ti ko fararọ ní ìpínlẹ̀ Ogun

Rotimi Paseda

Paseda
Àkọlé àwòrán, #BBCOGUNDEBATE: Èrò àwọn oludije ṣe ọtọ̀ọ̀tọ lóri ètò ẹkọ Ofẹ

Paseda ni ojutu ti oun ni lori abo ni pipada si ori ibi ti a ti bere.

O ni pipada si eto abo civil defence bi o senwa lati ipile ni ojuutu si isoro yii.

O ni pipada si eto abo iṣedale ti awon eeyan mo ni ona abayo

O salaye pé APC, APM ati PDP iru kankan naa ni won o si daa bi won se n ba ara won ja

Paseda ni Fifi oju isaju gbe ise agbase fun kongila lo n fa omiyale. O ni eni to ba gba ise akanse ibi ti omi ba ti yale yoo foju wina ofinomi

Gboyhega Nasiru

Gboyega Nasiru
Àkọlé àwòrán, #BBCGOVDEBATE: Ẹṣẹ Mẹ́ta ni ètò ìjọba fi lélẹ̀ ní Ogun

Gboyega ni pipada si ileewe ekosẹ ọwọ yoo wulo pelu ìmọ ẹrọ pẹlu kikọ awon eeyan ni iwa Omoluwabi ati idapada aṣa yoo yanju wahala abo.

Isiaka ni ona meji ni oro naa. Akoko ni olaju. O ni olaju maa n fa omiya sugbon ijoba gbodo mura fun un. O ni idasile eka ileese lati maa mojuto oro omiyale yoo wa.O ni eto idagbasoke naa n faa

Ademola Ogunbajo

Ademola Ogunbanjo
Àkọlé àwòrán, #BBCOGUNDEBATE: Èrò àwọn oludije ṣe ọtọ̀ọ̀tọ lóri ètò ẹkọ Ofẹ

Ogunbanjo ni omo ti ko ba ko iwe to yanju ko lee ri ise se.

O ni ọmọ Ogun kii ṣe ọ̀lẹ awon odo ipinle ogun lo mu won ya si yahooyahoo. O ni nipa atunto eko awon omo yahoo yoo lee sise ni stock exhange.

O ni awon yoo tun ro awon agbofinro lagbara.

Ogunbanjo ni aisi ato ilu nko ba oro omiyale. O ni bi a se n gbe ise agbase sita naa n faa

Adekunle Akinlade

Akinlade
Àkọlé àwòrán, #BBCGOVDEBATE: Ẹṣẹ Mẹ́ta ni ètò ìjọba fi lélẹ̀ ní Ogun

Akinlade ni ki ijoba to wa lode to de nnkan buru ju bayii lọ lóri abo. O ni ijoba to wa nikale bayii ti gbiyanju lori abo.

Ibeere lati ẹnu àwọn ará ilé

Awon ara ilú lásiko ti wọn gbọrọ lnu àwọn olùdíje
Àkọlé àwòrán, #BBCOGUNDEBATE: O ṣe pataki láti yan àwọn akanda ẹda si ipò kọmisọna.

Ibeere fun ogunbanjo: O ni ko ni iriri oselu ogun.

Bawo lo se fe see ti ikan ko fi ni ju ikan lo?

Idahun Ogunbanjọ: Iriri ninu oselu ko ni nnkan n se pelu ibi ti oro de duro bayii. O ni aisi idagbasoke ti ko jukan lo lo n fa ipe elekunjekun.

Okere ní oloju jinjin ti n mẹkun sún

"Ẹni to ba da ile NGO silẹ nítori òṣèlú O ni Jibiti ni" Ogunbanjọ