Asset declaration: Àwọn tó dipò ìlú mú tí wọ́n jẹ́jọ́ lórí dúkìa

Oríṣun àwòrán, NBA
Ofin orilẹ-ede Naijiria ni pe ẹnikẹni to ba di ipo ilu mu gbọdọ kede dukia rẹ labẹ ofin Naijiria ko to gori aleefa, bibẹẹkọ ẹni naa yoo foju wina ofin.
Iru nkan yii ti ṣẹlẹ si awọn oloṣelu ati awọn ọga agba kan lẹnu iṣẹ ijọba lorilẹ-ede Naijiria.
Eleyi to ṣẹlẹ laipẹ yii ni ti adajọ agba orilẹ-ede Naijiria Walter Onnoghen ti igbimọ CCB gbe lọ siwaju ile ẹjọ to n gbọ ẹsun aṣemaṣe awọn to dipo ilu mu lorilẹ-ede Naijiria, CCT lori ẹsun pe o kọ lati kede dukia rẹ.
Bayii, ijọba apapọ ti ni ki wọn ṣi fi silẹ naa ati pé ọpọlọpọ amofin lo gbà pé kò tọna lati

Oríṣun àwòrán, NBA
Ẹlomiran to tun jẹjọ lori iru ẹsun bayii ni Abẹnugan ile igbimọ aṣofin agba l'Abuja Bukola Saraki. Ẹ sun ti wọn fi kan Saraki ni pe irọ lo pa pẹlu dukia rẹ to kede.
Awọn agbẹjọro to le lọgọrun ti ẹ ṣoju Saraki lẹẹkan ṣoṣo nile ẹjọ nibi ti wọn ti n ṣe igbẹjọ ọhun.
Awọn wọnyi ti wọn dipo ilu mu ni wọn ti wọn si ti foju ile ẹjọ lori ẹsun pe wọn kọ lati kede

Oríṣun àwòrán, Fcaebook/Abubakar Bukola Saraki
Oloṣelu nla miran to tun jẹjọ niwaju CCT ni gomina Ipinlẹ Eko tẹlẹ ri, Bola Ahmed Tinubu. Wọn fẹsun kan Tinubu pé o pa irọ nigba to kede dukia rẹ nigba naa.

Oríṣun àwòrán, Twitter/APC
Ọga ile iṣẹ ifọpo rọbi Naijiria, NNPC ni wọn tun fẹsun kàn sẹyin pé ko ṣalaye.

Oríṣun àwòrán, NNPC















