You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Àwọn olùfẹ́hónúhàn dáná sun ọ̀pọ̀ ṣọ́ọ̀ṣì mẹ́ta àti mọ́ṣáláṣí ní Ethiopia
Awọn eeyan kan ti dana sun ọpọ ṣọọṣi ati mọṣalaṣi ni iha ariwa ati gusu Ethiopia.
Wahala naa bẹrẹ lẹyin ti awọn kan ti kọkọ ṣekupa ogun Musulumi, nigba ti ogunlọgọ awọn mii si farapa nibi eto isinku kan niluu Gondar, to wa lagbegbe Amhara.
Agbẹnusọ awọn Musulumi lorilẹ-ede naa sọ fun BBC pe mọṣalaṣi mẹrin ni wọn dana sun.
- Bíbéli mi ló sọ pé kí n fẹ́ ìyàwó omidan márùn ún, kìí ṣe ẹ̀ṣẹ̀- Pásítọ̀
- A ti yọwọ́ olùdíje méji kúrò láwo lẹ̀yìn àyẹ̀wò, wọn kò lè díje lábẹ́ àsíá ẹgbẹ́ PDP- David Mark
- Mínísítà Nàìjíríà, Abubakar Malami, tó wà nídí ẹjọ́ Sunday Igboho ti darapọ̀ mọ́ ìdíje dupò gómìnà Kebbi
- Ìdí nìyí tí Jonathan kò fi le díje dupò Ààrẹ Nàìjíríà mọ́
- Wo bí ètò Orò Ìje Oba Lamidi Adeyemi to wàjà ṣe lọ ní Oyo
- Ìjàmbá iná tó wáyé kò débi ibojì T. B. Joshua – Ilé ìjọsìn Synagogue
- Wo ohun tí o kò mọ̀ nípa Morenikeji Lasisi, olórí ẹrú tó ti bá Aláàfin mẹ́ta ṣiṣẹ́
- Ọmọ Ọba Charles kàn sí BBC lórí àjọ̀dún ọdún 90 tí BBC bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìròyín, Oríadé sọ̀rọ̀ pé..
- Ìj̀à tó bẹ́ sílẹ̀ ní Sudan ti gbẹ̀mí ènìyàn 200 lára àwọn tó sá àsálà fún ẹ̀mí wọn kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ ogun Janjaweed
Bẹẹ naa ni agbẹnusọ fun awọn ọmọlẹyin Kristi ṣalaye fun BBC pe wọn dana sun ṣọọṣi mẹta ni iha gusu orilẹ-ede naa.
Iroyin ni o ṣeeṣe ki iṣẹlẹ naa jẹ ẹsan fun awọn ogun Musulumi ti wọn ti kọkọ pa ṣaaju nibi eto isiniku to waye ni Amhara.
Ijọba orilẹ-ede naa ti sọ pe ọwọ awọn ti tẹ ọọdunrun ati aadọrin eeyan ti wọn funra si pe wọn lọwọ ninu rogbodiyan ọhun.
Wọn ni awọn ko fi ọwọ yẹpẹrẹ mu iṣẹlẹ naa, nitori naa awọn yoo fi imu ẹnikẹni ti ọwọ ba tẹ pe o n fa wahala lawọn ilu mi danrin.
Ẹwẹ, awọn Musulumi ni olu ilu orilẹ-ede naa, Addis Ababa ti n mura lati korajọ lọna ati fẹhonuhan lori ifẹmiṣofo naa.
Nnkan bii ida mẹrinlogoji ni awọn Musulumi to n gbe ni Ethiopia.