#U17WC: Mínísítà ní orí ìdúró l'òun ti wo ìfẹsẹ̀wọnsẹ̀ Nàìjíríà àti Hungary tán

Oríṣun àwòrán, Twitter/NFF
Ẹgbẹ agbabọọlu Naijiria ti ọjọ ori wọn ko ju ọdun mẹtadinlogun, the Golden Eaglets ya agbado ha si ọpọ lẹnu lẹyin ti wọn gbẹyẹ lọwọ ilẹ Hungary ninu idije ife ẹyẹ agbaye FIFA U-17 World Cup lorilẹede Brazil lalẹ ọjọ Satide.
Koda minisita fun ere idaraya ati ọrọ ọdọ, Sunday Dare sọ pe lori iduro l'oun ti wo ifẹsẹwọnsẹ naa to fi pari nitori ẹru.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 1
Nnkan ko kọkọ ṣẹnu 're fawọn ọjẹwẹwẹ Naijiria lẹyin ti Gyorgy Komaromi gba bọọlu sawọn fun ikọ agbabọọlu Hungary lẹyin iṣẹju mẹta ti ere bọọlu naa bẹrẹ.
- Ìgbẹ́ àá f'éwé! Chelsea fẹ́ Ajax dànú bí abẹ̀bẹ̀ nílé wọ̀n
- Arsenal sì wà lọ́mọ ìkókó lẹ́yìn ọdún mẹ́wàá- Patrice Evra
- "Ọ̀pọ̀ èèyàn ń bá mi ṣùn, ṣẹ́yún fún mi níbùdó ọmọ aláìgbọràn"
- Ambode, wá sọ tẹnu rẹ lọ́jọ́rùú lórí owó àwọn àkànṣe iṣẹ́ to ná - Ilé aṣòfin Eko
- Kíni ìdí ti àwọn ọmọ ogun fi n ṣọ́ àwọn Imaam ni Mecca?
- Bí nǹkan oṣù rẹ bá dáwọ́ dúró, àwọn ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọ rèé
Agbabọọlu Samson Tijani dayo naa pada nigba ti ifẹsẹwọnsẹ ọhun pe ogun iṣẹju.
Amọ, Samuel Major tun fọba lee fun Hungary lẹyin iṣẹju mẹjọ ki Usman Ibrahim to dayo naa pada eleyi to sọ di ọmi alayo mejimeji.
Oluwatimilehin Adeniyi lo fọba lee fun Naijiria nigba ti ere bọọlu ọhun ku iṣẹju mẹjọ ti yoo fi pari.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 2
Balogun Golden Eaglets, Tijani lo gba goolu ẹlẹẹkẹrin sawọn Hungary eleyi to jẹ ki Naijiria gbegba oroke pẹlu ami ayo mẹrin si meji.
Ẹwẹ, minisita ere idaraya ni o da oun loju pe ikọ agbabọọlu Naijiria yoo tubọ fakọyọ ninu ifẹsẹwọnsẹ wọn toku.
Minisita ṣalaye oun mọ pe awọn ọjẹwẹwẹ agbabọọlu Naijiria yoo fakọyọ ninu idije FIFA U-17 World nitori oun wo wọn nigba ti wọn n gbaradi niluu Abuja.












