Ìdí rèé tí àwọn ọ̀gágun tó lé ní 100 yóò kọ̀ ìwé fi ipò sílẹ̀

Oríṣun àwòrán, NDH
O kere tan awọn ọgagun agba to le ni ọgọrun ni ileeṣẹ ikọ ọmọogun orilẹede Naijiria yoo fi ipo silẹ tipatipa.
Idi ti eleyii yoo fi waye ni nitori awọn ọgagun ti aarẹ orilẹede Naijiria, Bola Ahmed Tinubu yan si ipo laipẹ yii.
Yatọ si awọn ti yoo fi iṣẹ wọn silẹ tipatipa yii, awọn ikọ ọmọogun miran yoo ma goke agba lẹnu iṣẹ wọn lati di awọn ipo ti awọn ọgagun to fi iṣẹ silẹ naa yoo di mu.
Eyi n waye lẹyin oṣu mẹfa ti awọn ọgagun agba mẹrinlelogun ati Ọgagun Brigadier general mejidinlogoji, ti wọn fi iṣẹ silẹ ni Oṣu Kejila, ọdun 2022, lẹyin ti wọn ti lo ọdun marundinlogoji ni ipo.
Iru igbeṣẹ yii wọpọ ni ileeṣẹ ọmọogun Naijiria, ti aarẹ ba ti yan olori ikọ ọmọogun si ipo adari, gbogbo awọn to jẹ ọga rẹ yoo fi ipo silẹ nitori wọn ko ni lee maa gba aṣẹ lọwọ rẹ.
Awọn ti yoo faragba ninu fifi iṣẹ ọmọogun silẹ ni tipatipa ni awọn to wa ni kilasi 36, 37 ati 38 ti wọn ti bẹrẹ iṣẹ ṣaaju adari tuntun naa abi ti wọn jọ wa ni kilasi kan naa.
Kini awọn onimọ nipa ikọ ọmọogun sọ?

Oríṣun àwòrán, NDH
Awọn onimọ nipa ikọ ọmọogun bii Ọgagun ajagun fẹyinti, Sadik Garba ni bio tilẹ jẹpe iru igbeṣẹ yii wọpọ ni ẹka ileeṣẹ ologun, amọ o ma n fi alafo silẹ lọpọ.
Garba ni awọn ọgagun ti yoo kuro naa yoo lọ pẹlu imọ wọn, eleyii ti yoo fi alafo silẹ nitori ipo ti wọn dimu.
O ni ni ọdun yii nikan, ikọ ọmọogun to jẹ ọgagun aadọje ni yoo fi ipo wọn silẹ, eleyii ti yoo fi ọpọ alafo silẹ nipa ọgbọn, imọ ati iriri ti wọn ti ni lẹnu iṣẹ.
Bakan naa lo ni ipalara ni eyi yoo jẹ fun Naijiria nitori iye ti orilẹede Naijiria ti na le wọn lori ati iye ọdun to yẹ ki wọn ṣi lo ni ipo lati fi ṣiṣẹ.












