Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́

Àkọlé fọ́nrán ohùn, Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́
Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 1

Ẹ ye gberoyin ofege kiri!

Awọn wo lo n baa wi?

Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Oyo lo n kilọ fawọn to n pin fidio kan

Eyi to n ṣafihan bi Boko Haram ṣe gbiyanju lati ya wọ ipinlẹ naa

Ileeṣẹ ọlọpaa ni irọ to jinna si ootọ ni fidio yii, ati pe...

Ati pe kinni?

Lọ ka iyoku lori ikanni BBC Yoruba

''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''

Níbo ni King Sunny Ade wà gan an?

Bi ti bawo, ṣe agbaọjẹ olorin Juju sọnu ni?

Bẹẹ la a bi ni o, ọkan lara awọn ọmọbìnrin gbajugbaja akórin naa lo ké gbàjarè bẹẹ lórí ayélujára

Koda, o tun fẹsun kan ọkan lara ọmọkunrin baba rẹ pe oun lo gbe baba awọn pamọ

Amọ, ẹbi KSA ti fidi rẹ mulẹ pe ṣaka lara baba da

Kan soju opo BBC Yoruba fun ẹkunrẹrẹ

''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''

Ajọ EFCC to n gbogun tiwa ibajẹ ti fọwọ ṣinkun ofin mu gbamujọ E-Money niluu Eko

Lori ẹsun pe o takubu owo naira eyi to lodi sofin orilẹede Naijiria

Lalẹ ọjọ Aje ni wọn mu E-Money nile rẹ l'Eko

EFCC ni yoo foju ba ile ẹjọ ti iṣẹ iwadii ba ti pari lori ọrọ rẹ