Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́

Àkọlé fọ́nrán ohùn, Àkójọpọ̀ àwọn ìròyìn kò ṣeé má gbọ̀ọ́ káàkiri Naijiria àti àgbáyé
Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 2

Gbogbo igbesẹ ti ijọba mi n gbe lori eto ọrọ aje Naijiria ti n so eso rere

Ààrẹ Bola Tinubu lo sọ bẹẹ lónìí àyájọ́ ọdún kejì ìjọba rẹ̀

Kinni aarẹ wa sọ lori ọwọngogo ounjẹ ati epo bẹntiroolu?

Alaye wa lori ikanni BBC Yoruba

''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''

Áṣiri tu!

Aṣiri ki lo tu?

Mamman Ali Ọmọ alaga ẹgbẹ oṣelu PDP telẹ, Ahmadu Ali, lo ma ti rẹwọn ọdun mẹrinla he

lẹyin to jẹbi ẹsun lilu ijọba ni jibiti owo to le ni biliọnu meji naira owo iranwọ epo bẹntiro

Mamman ati ẹnikeji rẹ, Christian Taylor, nile ẹjọ dajọ ẹwọn fun

ile ẹjọ tun ni ki ijọba gbẹsẹ le gbogbo dukia ti wọn fowo jibiti naa ko jọ

Ẹkunrẹrẹ iroyin naa wa loju opo BBC Yoruba

'''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''''

Ariwo sọ lori ayelujara lalẹ ana Ọjọru

Ki lo fa ariwo ọhun?

Nitori àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tó maa ń ṣe ìdánwò WAEC nínú òkùnkùn ma ni

Ọ̀kan lára àwọn akẹ́kọ̀ọ́ naa sọ fun BBC Yoruba wi pe

O to aago mẹ́ta ọ̀sán kawọn to bẹrẹ idanwo to yẹ kawọn ti bẹrẹ lati ago mẹsan taarọ