Secondus visits Obasanjo: Nítorí wàhálà tó ń wáyé lẹ́gbẹ́ òṣèlú rẹ̀, Uche Secondus, alága PDP mórílè ilé ààrẹ tẹ́lẹ̀, Olusegun Obasanjo

Uche Secondus atawọn ọmọ ikọ rẹ

Oríṣun àwòrán, dailytrust

Alaga ẹgbẹ oṣelu PDP, Ọmọọba Uche Secondus ti gunlẹ si ilu Abẹokuta nile aarẹ orilẹede Naijiria nigbakanri, Oloye Oluṣẹgun Ọbasanjọ.

Ni nnkan bii agogo mejila ni Secondus gunlẹ, ti ọpọ si n woye pe abẹwo alaga apapọ PDP naa ko yẹ lori wahala to n lu agogo jo laarin ẹgbẹ oṣelu naa bayii.

Lọwọ yii, Secondus n ja fitafita lati di ipo rẹ mu gẹgẹ bi alaga ẹgbẹ oṣelu naa lẹyin ti awọn eekan kan laarin ẹgbẹ oṣelu naa n sọ fun un pe ile to lọ, ko fi ipo silẹ.

Gbogbo akitiyan awọn agbaagba ẹgbẹ oṣelu naa lati bomi pa ina wahala naa ni ko tii ba ọwọ rere jade.

Ohun ti o han si gbogbo eniyan ni pe Oloye Ọbasanjọ ti fa kaadi ọmọ ẹgbẹ rẹ ya to si ti juwọ si ẹgbẹ oṣelu PDP, amọṣa gẹgẹ bi ẹni to fi ọdun mẹjọ jẹ aarẹ alagbada labẹ aburada ẹgbẹ oṣelu naa, ọpọ onwoye lo n woo pe ko ni ṣai ni ipa to loorin laarin awọn eekan ọmọ ẹgbẹ oṣelu naa.

Àkọlé fídíò, Kola Ologbondiyan: PDP ni yóò mú ọmọ Nàíjíríà kúrò lóko ìyà tí wọn wà ní 2023