You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Marwa NDLEA: Ta ni Mohammad Buba Marwa tó ṣẹ̀ṣẹ̀ di ọ̀gá àgbà àjọ NDLEA?
Wo àwọn ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa Mohammad Buba Marwa tó ṣẹ̀ṣẹ̀ di ọ̀gá àgbà àjọ NDLEA.
Mohammad Buba Marwa ni ọga agba tuntun ti ìjọba apapọ ṣẹṣẹ Yan fún ajo to n gbogun ti lilo egbogi oloro ni Naijiria, NDLEA.
Nigba to bẹrẹ iṣẹ ni ọọfisi rẹ tuntun, lọjọ Aje, o ni o jẹ ohun tó n kọ òun lominu pe pupọ nínú àwọn ọdọ Naijiria lo n lo egbogi oloro.
- Adigunjalè 24 tó ń jí epo rọ̀bì la mú ní Ondo- Ikọ̀ ọmọogun orí omi
- Sunday Igboho fún Fulani Oyo ní gbèǹdéke, Seriki fulani yarí, ọlọ́pàá dá síi...
- Wo ìpalára ní ọ̀nà mẹ́fà tó lè bá ènìyàn tí kò bá kí ń mu omi mímu tó ìwọn tó yẹ
- Ọlọ́pàá mẹ́rin kú, ọ̀kan dàwátì níbí ìkọlù tó wáyé ní Birnin-Gwari ní ìpínlẹ̀ Kaduna- Ọga Ọlọ́pàá
Marwa sọ pé "nnkan bíi 14.1 mílíọ̀nù ọmọ Naijiria lo n lo oriṣiriṣi oogun oloro."
Gẹgẹ bó ṣe sọ, iye ọjọ orí awọn tó n lo oogun náà jẹ láti ọdún marundinlogun sí mẹrinlelọgọta, lẹyin naa ló ṣèlérí pé adinku yóò dé bá iye èèyàn náà labẹ idari ohun.
Ta ni Mohammad Buba Marwa?
Wọn bí Mohammad Buba Marwa ni ọjọ kẹsán án, oṣù Kẹsán án, ọdún 1953.
O wa lati ìjọba ìbílẹ̀ Michika, ni ipinlẹ Adamawa.
Buba Marwa kawe ni ile ẹkọ awọn ologun to wa ni Zaria, nipinlẹ Kaduna.
Lẹyin naa ló tẹkọ leti lọ sí Pittsburgh, nibi to ti kọ ẹkọ nipa ìmọ ibaṣepọ laarin awọn orilẹ-ede, ko to gboye síi nipa ìmọ eto ìlú ní Fasiti Harvard.
Awọn ibi to ti ṣiṣẹ sẹyin:
O ṣiṣe gẹgẹ bíi gomina ipinlẹ Bornu labẹ ijoba ologun lọdun 1992, ìyẹn nigba ti ọgagun Ibrahim Babangida jẹ Ààrẹ.
Òun tun ni gomina ipinlẹ Eko lọdun 1996 nigba ti ọgagun Sani Abacha jẹ Ààrẹ ologun.
Ni 2003, Marwa fi ipo rẹ silẹ gẹgẹ bíi alaga àti Olùdarí ileeṣẹ ọkọ ofurufu Albarka Airlines.
- Fulani kìí ṣe ajínigbé! Akeredolu kò ní ká pòórá nínú igbó ìjọba l'Ondo, ọhun tí Gómìnà sọ rèé...- Miyetti Allah
- Tírélà agbépo bẹntírò gbiná nílùú Abeokuta, ọkọ̀ mérin jóná ráúráú
- Gbogbo ẹ̀yin Fulani darandaran tó wà ní ìgbó ìjọba ní Ondo, ọjọ méje lẹní láti pòórá - Gomina Akeredolu
- Ó lé ní ọgọ́rin èèyàn tó kú nínú ìjà ẹlẹ́yàmẹ́yà tó wáyé ní Dafur- Aláṣẹ Sudan
Loṣu Kejìlá ọdún 2006, o kede pe òun fẹ du ipo ààrẹ labẹ àsìá ẹgbẹ òṣèlú PDP, ṣugbọn o fìdí janlẹ, èyí tó mú kó ṣegbe lẹyin Umaru Musa Yar'Adua to padà di Ààrẹ.
Ni 2007, Marwa di aṣojú Naijiria sí orilẹ-ede South Africa.
Lọdun 2011 o gbe àpótí ipo gomina labẹ àsìá ẹgbẹ Congress for Progressive Change, CPC, nipinlẹ Adamawa, ṣugbọn o tun fidi janlẹ.
Lẹyin-o-rẹyin, Marwa darapọ mọ ẹgbẹ òṣèlú APC lọdun 2015 lẹyin tí wọn búrawọle fún Ààrẹ Muhamadu Buhari.
- Sunday Igboho fún Fulani Oyo ní gbèǹdéke, Seriki fulani yarí, ọlọ́pàá dá síi...
- Wo ìpalára ní ọ̀nà mẹ́fà tó lè bá ènìyàn tí kò bá kí ń mu omi mímu tó ìwọn tó yẹ
- Ọlọ́pàá mẹ́rin kú, ọ̀kan dàwátì níbí ìkọlù tó wáyé ní Birnin-Gwari ní ìpínlẹ̀ Kaduna- Ọga Ọlọ́pàá
- Adigunjalè 24 tó ń jí epo rọ̀bì la mú ní Ondo- Ikọ̀ ọmọogun orí omi