Lagos Okada ban: 'Ọ̀kadà gígùn ni mo fi bọ́ ọmọ àti ìyàwó'

Àkọlé fídíò, 'Ọwọ́ tó bá dilẹ̀ ni èṣù ń bl ní iṣẹ́kíṣẹ́'

Ọwọ to dilẹ, l'Eṣu maa n bẹ ni iṣẹkiṣẹ. Eyi ni ọrọ ọkan lara awọn ọlọkada niluu Eko, Oladejo Adetunji lori igbesẹ ijọba lati fofin de alupupu ti ọpọ mọ si ọkada ati kẹkẹ ẹlẹsẹ mẹta.

Ṣaaju ọjọ kinni oṣu keji ọdun 2020 ti eto naa yo gbera sọ, Ọgbẹni Adetunji sọ pe ofin ti ijọba gbe kalẹ yii dabi ẹni pe ijọba gba ẹmi lẹnu awọn ni.

O ṣalaye pe ko si ọna mii ti oun mọ lati fi wa ounjẹ ọjọọ ti oun yoo fi bọ idile oun, ati wi pe ijọba gan an ko pese iṣẹ miiran fawọn ko to fofin de ọkada gigun.

Ọgbẹni Adetunji rọ ijọba lati tun ero rẹ pa lori igbesẹ rẹ ki o si wa ọna mii ti yoo mu irọrun ba awọn ara ipinlẹ Eko.