Sugar: Iléẹjọ́ ní àwọn afurasí mẹ́rin kò mọwọ́-mẹsẹ̀ lórí ikú Sugar

Temitope Olatoye

Oríṣun àwòrán, Temitope Sugar

Ileẹjọ giga to wa nilu Ibadan ti da awọn afurasi mẹrin silẹ, awọn ti wọn n jẹjọ lori iku to pa asoju-sofin to n soju ẹkun idibo Lagelu Akinyẹle nipinlẹ Ọyọ, Asofin Temitọpẹ Olatoye, ti gbogbo eeyan mọ si Sugar,

Awọn afurasi naa ni Akinmoyede Olafioye, to jẹ akojanu ile tẹlẹ nile asofin ipinlẹ Ọyọ ati Rafiu Adebayọ, to fi mọ Rasheed Ọladele ati Kazeem Ayinde.

Adajọ Adegbọla Mufutau, lasiko to n gbe idajọ rẹ kalẹ kede pe awọn olujẹjọ naa ko lẹsẹ lọrun nitori ikọ olupẹjọ kuna lati fidi ẹri to daju mulẹ pe awọn olujẹjọ ọhun jẹbi ẹsun ipaniyan.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Bẹẹ ba gbagbe, Asofin Temitope Olatoye Sugar lawọn eeyan kan sekupa lọjọ Satide, ọjọ Kẹsan osu kẹta ọdun 2019 lasiko idibo gomina ati tile asofin ipinlẹ to waye yika orilẹede wa Naijiria.

Àkọlé fídíò, Àwọn aladugbo ibí tí ìjọba Èkó tí n wole sọ èrò ọkàn wọn

Nigba to n fesi lori idajọ naa, Asofin Akinmoyede ni Ọlọrun ti da oun lare lori awọn ẹsun ipaniyan ti wọn fi kan oun lori iku Sugar, ti otitọ si ti foju han pẹlu idajọ naa pe oun ko mọwọ mẹsẹ ninu awọn ẹsun ti wọn fi kan oun.

Àkọlé fídíò, Ẹgbọ́n olóògbé Suga: Wọ́n yìnbọn fún Suga lójú mi, n kò sì lè dá wọn dúró

Olafioye wa lo akoko naa lati kẹdun pupọ pẹlu awọn mọlẹbi oloogbe ọhun, pẹlu adura pe Ọlọrun yoo tu wọn ninu lati gba adanu naa mọra.