Blackout: Iléeṣẹ́ amúnáwá ní ìṣẹ́ ti ń lọ láti ṣe àtúnṣe ẹ̀rọ náà

Oríṣun àwòrán, @ayemojubar
Ẹrọ amunawa apapọ fun orilẹede Naijiria dẹnukọlẹ lọjọbọ oni, eyi to ko orilẹede Naijiria sinu okunkun biribiri fun igba akọkọ lọdun 2020.
Ileesẹ amunawa TCN fidi isẹlẹ naa mulẹ loju opo Twitter rẹ, eyi to wipe "ni deede aago kan ku isẹju mẹrindinlọgbọn lọsan oni ni aise deede ba ẹrọ amunawa to n pese ina ọba ni Naijiria, eyi to sọ awọn agbegbe kan si okunkun biribiri."
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- N kò jẹ Mayegun láti bùgá, mo wá tún ilẹ̀ Yorùbá ṣe ni - Wasiu Ayinde
- Ọta ìbọn ogun Biafra ṣì wà lọ́rùn mi lẹ́yìn àádọ́ta ọdún tí ogun parí - Umar
- Ìtàn ìgbé ayé Bode Thomas rèé, ó kọ́ wa láti máa kó ẹnu wa ní ìjánu
- Ìyàwó gómìnà tọ́jọ́ orí rẹ̀ kéré jù ní Nàìjíríà rèé, ohun tóo lè fẹ́ mọ̀ nípa rẹ̀
- Ìyàtọ̀ wo ló wà láàrin Amotekun àtàwọn àjọ aláábò mìíràn
- Obasanjo, Makinde ṣèpàdé bòńkẹ́lẹ́ lórí ìhà tí ìjọba àpapọ̀ kọ sí Amotekun
Atẹjade ori ayelujara naa ni "amọ nigba to di ago kan kọja isẹju mẹwa ni ina ọba pada silu Abuja atawsn agbegbe mii to kan. A si n sisẹ lọwọ lori ẹrọ amunawa to dẹnu kọlẹ naa, ki ina ọba lee duro pada yika Naijiria."
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 1

Oríṣun àwòrán, @ayemojubar
Bakan naa ni ileesẹ amunawa to wa ni agbegbe Ikeja nilu Eko sọ loju opo Twitter rẹ pe ẹrọ amunawa ni Naijiria bajẹ ni aago meji kọja isẹju mẹẹdogun lssan oni Ọjọbọ, lẹyin isẹlẹ akọkọ to waye.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 2
"Ẹyin onibara wa, aayan ti n lọ lati se atunse ẹrọ naa, ẹ jọwọ, ẹ ba wa fara daa."
Bẹẹ ba gbagbe, o to igba mẹwa ti ẹrọ amunawa to n pese ina ọba yika orilẹede Naijiria bajẹ lọdun 2019.









