Ooni: Mo rọ àwọn àgbẹ̀ àti darandaran láti gba ìrẹ́pọ̀ láàyè

Oríṣun àwòrán, Ooni of Ife
Ọọni tilu Ile Ifẹ, Ọba Adeyẹye Ẹnitan Ogunwusi Ọjaja Keji, ti rawọ ẹbẹ si awọn agbẹ ati darandaran lati wa ni irẹpọ, ki ounjẹ lee tubọ buyaari fun wa.
Aba Adeyẹye, ẹni to parọwa yii ni aafin rẹ lasiko ayẹyẹ ọdun isu tuntun tun sọ pe, ti ọwọn gogo ounjẹ ba fi wa nitori ija awọn agbẹ ati darandaran, a jẹ pe a n kọ lẹta ipe fun aisan ni.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Dangote, jọ̀ọ́ nawọ́ ìrànwọ́ láti dá iléeṣé sílẹ̀ fún wa ní Ọyọ - Aláàfin rawọ́ ẹ̀bẹ̀
- Ọ̀ṣun Òṣogbo 2019 bẹ̀rẹ̀, àwọn iléeṣẹ́ àdáni ń bèèrè fún ẹ̀rọ ìgbàlódé láti sàfihàn àjọ̀dún
- Ó tó gẹ́ẹ́! Àsìkò tó láti fi ìwọ́de gba ara wa sílẹ̀ lọ́wọ́ ebi àti oko ẹrú - Sowore
- Ìjọba Buhari ń wùwà bíi ìjọba Abacha lórí ọ̀rọ̀ Ṣoworẹ- Ṣoyinka
- Iléẹjọ́ gba onídùròó El-Zakzaky, ó ní kó lọ gba ìtọ́jú lókè òkun
O ni ounjẹ aṣara loore nikan lo lee le aisan jinna si agọ ara wa.
Ọba Ogunwusi ni laipẹ ni wọn yoo pada si ohun to n waye ni atijọ nidi dida awọn ọja tuntun silẹ si ni ilu Ile Ifẹ.

Oríṣun àwòrán, Ooni of Ife
Ọọni Ifẹ ni ọja Ejigbo Mẹkun ti wa lati ẹẹdẹgbẹta ọdun sẹyin, bi wọn si se se agbende rẹ pada ni ọdun yii se afihan ohun rere to n bọ.








