Organisation of Islamic Cooperation: Àǹfààní wo ló wà nínú ẹgbẹ́ OIC?

Awọn ẹgbẹ OIC

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Àkọlé àwòrán, OIC n ṣepade
Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 2

Wọn da ẹgbẹ Organisation of Islamic Cooperation ti ọpọ mọ si OIC silẹ lọdun 1969 pẹlu orilẹede mẹtadinlọgọta.

Ọrilẹede mẹtalelaadọta ninu awọn orilẹede to jẹ ọmọ ẹgbẹ OIC lo jẹ awọn orilẹede ti awọn ẹlẹsin musulumi ti pọ ju.

Ẹgbẹ OIC ni aṣoju ni ajọ iṣọkan agbaye ati ajọ ilẹ alawọfunfun ti wọn n pe ni European Union.

Àkọlé fídíò, Nigeria Population: Báwọn ọmọ Nàíjíríà ṣe ń pọ̀ si jẹ́ ìpèníjà fún Buhari

Kinni erongba OIC?

Gẹgẹ bi adehun ti wọn ṣe, ẹgbẹ OIC pinnu lati maa gbe ohun to jẹ mọ ẹsin musulumi larugẹ lawọn orilẹede to jẹ ọmọ ẹgbẹ naa.

Ẹgbẹ OIC tun pinnu pe awọn yoo ṣe imugbooro aṣa ati imọ sayẹnsi lawọn orilẹede to jẹ ọmọ ọhun.

OIC tun pinnu lati mu eto aabo lọkun-kundun ati lati lepa alaafia kaakiri gbogbo orilẹede ti ẹgbẹ naa wa.

OIC tun pinnu lati maa ṣe igbelarugẹ eto ẹkọ imọ-ijinlẹ ni gbogbo orilẹede to jẹ ọmọ ẹgbẹ naa.

Akitiyan OIC lori awọn to ṣatipo

Ẹgbẹ OIC ti gbalejo awọn atipo bi miliọnu mejidinlogun lati igba ti ẹgbẹ ọhun ti wa titi di ọdun 2010

Awọn orilẹede to jọ ọmọ ẹgbẹ OIC ti n gbalejo awọn atipo lati awọn orilẹede ti rukerudo ti n ṣẹlẹ lati ọdun 2010

Ami OIC

Oríṣun àwòrán, Wilkipedia

Àkọlé àwòrán, Kinni o mọ nipa OIC?

Lọdun 2011 ni ẹgbẹ OIC yi orukọ rẹ pada Organisation of Islamic Conferencde ssi Organisation of Islamic Cooperation.

Buhari mórí lé Saudi lẹ́yìn ìbúrawọlé fún sáà kejì

Lẹyin iburawọle fun saa keji l'Ọjọru, Aarẹ Muhammadu Buhari mo ri le orilẹ-ede Saudi Arabia lonii Ọjọbọ.

Muhammadu Buhari

Oríṣun àwòrán, Facebook/Femi Adesina

Àkọlé àwòrán, Aarẹ Muhammadu Buhari n lọ fun ipade OIC

Aarẹ n lọ fun apero ẹgbẹ Organisation of Islamic Cooperation ti ọpọ mọ si OIC ti yoo waye lọjọ Ẹti niluu Makkah.

Skip X post, 1
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 1

Ọjọ keji, oṣu kẹfa ni Aarẹ Buhari yoo pada si orilẹ-ede Naijiria.

Àkọlé fídíò, Nigeria Population: Báwọn ọmọ Nàíjíríà ṣe ń pọ̀ si jẹ́ ìpèníjà fún Buhari

Ninu atẹjade ti oludamọran agba fun aarẹ lori ọrọ iroyin, Garba Shehu sita, Aarẹ Buhari yoo sọrọ nibi apero ọhun.

Atẹjade naa sọ pe aarẹ yoo sọrọ lori iṣepataki ki awọn orilẹ-ede to jẹ ọmọ ẹgbẹ OIC wa ni iṣọkan lati le jọ koju ipenija bi awọn agbesumọmi ti wọn n da rogbodiyan kalẹ kaakiri.

Aarẹ Buhari yoo tun sọrọ lori anfaani to wa nibi idokowo awọn orilẹ-ede ilẹ okere ni Naijiria.

Àkọlé fídíò, Àgbà ni Obasanjo, oun tó ń sọ yé e, ìjọba ni kó tají - Wale oke

Buhari ni aarẹ orilẹ-ede Naijiria kẹta ti yoo lọ fun apero ẹgbẹ OIC lẹyin oloogbe aarẹ tẹlẹ ri, Umaru Yar'Adua ati aarẹ ana, Goodluck Jonathan ti kọkọ lọ fun irun apero bẹẹ.

Skip X post, 2
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 2

Gomina ipinlẹ Jigawa, Mohammed Badaru Abubakar, Gomina Oṣun, Gboyega Oyetola ati Gomina ipinlẹ Niger, Abubakar Sani Bello wa lara awọn ti yoo kọwọ rin pẹlu aarẹ lọ ilẹ Saudi.

Àkọlé fídíò, Ẹni bá láyà kó wá wọ̀ọ́! Ta ni Ìgè Àdùbí nílẹ̀ Oodua?