Organisation of Islamic Cooperation: Àǹfààní wo ló wà nínú ẹgbẹ́ OIC?

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Wọn da ẹgbẹ Organisation of Islamic Cooperation ti ọpọ mọ si OIC silẹ lọdun 1969 pẹlu orilẹede mẹtadinlọgọta.
Ọrilẹede mẹtalelaadọta ninu awọn orilẹede to jẹ ọmọ ẹgbẹ OIC lo jẹ awọn orilẹede ti awọn ẹlẹsin musulumi ti pọ ju.
Ẹgbẹ OIC ni aṣoju ni ajọ iṣọkan agbaye ati ajọ ilẹ alawọfunfun ti wọn n pe ni European Union.
Kinni erongba OIC?
Gẹgẹ bi adehun ti wọn ṣe, ẹgbẹ OIC pinnu lati maa gbe ohun to jẹ mọ ẹsin musulumi larugẹ lawọn orilẹede to jẹ ọmọ ẹgbẹ naa.
Ẹgbẹ OIC tun pinnu pe awọn yoo ṣe imugbooro aṣa ati imọ sayẹnsi lawọn orilẹede to jẹ ọmọ ọhun.
OIC tun pinnu lati mu eto aabo lọkun-kundun ati lati lepa alaafia kaakiri gbogbo orilẹede ti ẹgbẹ naa wa.
OIC tun pinnu lati maa ṣe igbelarugẹ eto ẹkọ imọ-ijinlẹ ni gbogbo orilẹede to jẹ ọmọ ẹgbẹ naa.
Akitiyan OIC lori awọn to ṣatipo
Ẹgbẹ OIC ti gbalejo awọn atipo bi miliọnu mejidinlogun lati igba ti ẹgbẹ ọhun ti wa titi di ọdun 2010
Awọn orilẹede to jọ ọmọ ẹgbẹ OIC ti n gbalejo awọn atipo lati awọn orilẹede ti rukerudo ti n ṣẹlẹ lati ọdun 2010

Oríṣun àwòrán, Wilkipedia
Lọdun 2011 ni ẹgbẹ OIC yi orukọ rẹ pada Organisation of Islamic Conferencde ssi Organisation of Islamic Cooperation.
Buhari mórí lé Saudi lẹ́yìn ìbúrawọlé fún sáà kejì
Lẹyin iburawọle fun saa keji l'Ọjọru, Aarẹ Muhammadu Buhari mo ri le orilẹ-ede Saudi Arabia lonii Ọjọbọ.

Oríṣun àwòrán, Facebook/Femi Adesina
Aarẹ n lọ fun apero ẹgbẹ Organisation of Islamic Cooperation ti ọpọ mọ si OIC ti yoo waye lọjọ Ẹti niluu Makkah.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 1
Ọjọ keji, oṣu kẹfa ni Aarẹ Buhari yoo pada si orilẹ-ede Naijiria.
Ninu atẹjade ti oludamọran agba fun aarẹ lori ọrọ iroyin, Garba Shehu sita, Aarẹ Buhari yoo sọrọ nibi apero ọhun.
Atẹjade naa sọ pe aarẹ yoo sọrọ lori iṣepataki ki awọn orilẹ-ede to jẹ ọmọ ẹgbẹ OIC wa ni iṣọkan lati le jọ koju ipenija bi awọn agbesumọmi ti wọn n da rogbodiyan kalẹ kaakiri.
Aarẹ Buhari yoo tun sọrọ lori anfaani to wa nibi idokowo awọn orilẹ-ede ilẹ okere ni Naijiria.
Buhari ni aarẹ orilẹ-ede Naijiria kẹta ti yoo lọ fun apero ẹgbẹ OIC lẹyin oloogbe aarẹ tẹlẹ ri, Umaru Yar'Adua ati aarẹ ana, Goodluck Jonathan ti kọkọ lọ fun irun apero bẹẹ.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 2
Gomina ipinlẹ Jigawa, Mohammed Badaru Abubakar, Gomina Oṣun, Gboyega Oyetola ati Gomina ipinlẹ Niger, Abubakar Sani Bello wa lara awọn ti yoo kọwọ rin pẹlu aarẹ lọ ilẹ Saudi.















