Olè Lekki: Obìnrin méjì ni wọ́n dá lọ́nà, tọ́wọ́ ọlọ́pàá fi tẹ̀ wọ́n

Oríṣun àwòrán, @policeNG
Yoruba ni ọjọ gbogbo ni ti ole, amọ ọjọ kansoso pere ni ti olohun.
Bẹẹ lọrọ ri fun awọn ole meji kan nipinlẹ Eko, nigba ti ọwọ palaba wọn segi, ti akara wọn si tu sepo.
Awọn firi nidi ọkẹ naa, ti wọn gbajugbaja fun isẹ alọnilọwọgba lagbegbe Lekki, ni wọn pe oruk wọn ni Adebayọ Ayọmide ati Isaac David.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- INEC-Àwọn jándùkú àti ọmọ ilé ìṣẹ́ ológun lo dá ètò ìdìbò Gómìnà Rivers rú
- Wike fẹ́ lò wá láti da ìdìbò rú pẹ̀lú rìbá - Iléeṣẹ́ ológun
- APC gba ìjòkò tó pọ̀ jùlọ ní ilé aṣòfin àgbà
- A tún ti ṣàwárí omi àjèjì míràn ní Ilé-Ifẹ̀ - Ọọ̀ni
- Òkùnkùn biribiri ni ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ ìjọba ìbílẹ̀ mẹ́fà nílẹ̀ Ìjẹ̀ṣà tó na òṣìṣẹ́ àjọ amúnáwá
- Bàbá pokùnso ní àhámọ́ lórí ẹ̀ṣùn pé ó bá ọmọ rẹ̀ lòpọ̀
Aago mẹsan alẹ ni ikọ ọtẹlẹmuyẹ, ti ọga ọlọpa kan lati agọ ọlọpa Marọkọ, Isah Abdulmajid ko sodi, lọ paraaro afara kan to so adugbo Lekki pọ mọ Ikoyi, asiko yii si ni wọn ri awọn omidan meji kan, ti wọn n gbọn jinni-jinni.
Nigba ti wọn beere lọwọ awọn ọmge naa pe, ki lo se wọn, ni wn ba salaye pe awọn alọkolohunkigbe meji lo fi ibọn gba ohun ini awọn, ti wọn si tọka ọna tawọn ole ọhun morile fun awọn ọlọpa.
Ọwọ sinkun awn ọlọpa yii ba awọn ole naa, ti wọn si ba ibọn ilewọ kan, ada ati ọpọ ẹrọ ibaraẹnisọrọ alagbeka lọwọ wọn.
Nigba ti wọn n ka ni agọ ọlọpaa, awọn ole naa ni ara ọmọ ẹgbẹ ikọ adigunjale kan ti wọn n da agbegbe Lekki laamu ni awọn.

Oríṣun àwòrán, @WeArePindula
Nigba to n gbosuba fun ikọ ọlọpa to se bẹbẹ yii, Kọmisana ọlọpa nipinlẹ Eko, Zubairu Muazu wa pasẹ pe ki wọn gbe ẹsun awọn ole meji ọhun sabẹ ikọ to n gbogun ti iwa idigunjale nipinlẹ Eko fun iwadi kikun.
Muazu wa fọkan awọn olugbe ipinlẹ Eko balẹ pe ileesẹ ọlọpa mu aabo ẹmi ati dukia wọn lọkunkundun, to si tun fewe ọmọ mọ awọn ọdaran leti lati tun ero wọn pa, bibẹẹkọ ikoko ko ni gba omi, ko gba ẹyin, ko tun gba ṣọṣọ.













