2019 El;ections: Ìjàmbá iná tó ń wáyé lemọ́lemọ́ ń kọ àjọ INEC lóminú

Oríṣun àwòrán, Tvc
Ajọ eleto idibo INEC ti sọ pe, ẹrọ to n yẹ kaadi idibo wo, to din diẹ ni ẹgbẹrun marun lo jona ni ọfiisi ajọ naa to wa nilu Awka nipinlẹ Anambra lọjọ iṣẹgun.
Amọṣa, ajọ INEC ni eyi ko lee pagidina aṣeyọri eto idibo apapọ to n bọ lọna.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Aranṣọ, olórin àti àwọn mì í ti ko fẹ́ kí ìdìbò kásẹ̀ nílẹ̀ ní Nàìjíríà
- Ìjìyà Amosun n dúró dè é di ẹ̀yìn ìdìbò - APC
- Inec: Kò sí ìká tí o kò lè fí dìbò, ṣáà tí tẹ̀ ẹ́ sójú ẹ dáadáa
- Ìjọba àpapọ̀ fẹ́ dènà lílo ayélujára àti ẹ̀rọ ìbáraẹnisọ̀rọ̀ lọ́jọ́ ìbò - Fayose
- Bí ọkọ mi bá fìdírẹmi, màá gbà f'Ọ́lọ́run - Titi Abubakar
- Ajọ UN ati INEC gbé ìlanilọ́yẹ̀ lọ Kwara
- Ọ̀rọ̀ bọ́ lórí òjò òkò tó rọ̀ lé àwọn asaájú APC l‘Abeokuta
- Ẹfunroye Tinubu - Ògbóǹtagí oníṣòwò, olówò ẹrú àti afọbajẹ
- Olúwa mi, n kò jẹ̀bí ẹ̀sùn àjẹbánu - Babachir Lawal
Ninu atẹjade kan eyii ti Amofin Festus Okoye, to jẹ Kọmiṣọna agba feto iroyin ati idanilẹkọ labẹ ajọ Inec fisita fawọn oludibo, o ni ajọ INEC iwadi ti bẹrẹ lori to ohun to fa ijamba ina to jo awọn ohun elo idibo ọhun.
O ni ajọ INEC ti gbe igbesẹ lori kiko awọn kaadi idibo to ku lawọn ipinlẹ miran wa si ipinlẹ Anambra.
"Eyi ni ẹlẹẹkẹta irufẹ iṣẹlẹ ijamba ina yii ti yoo maa waye laaarin ọjọ mejila, lẹyin eyi to waye lawọn ọfiisi ajọ naa ni ijọba ibilẹ Isiala Ngwa nipinlẹ Abia ati Qua'an Pan ni ipinlẹ Plateau.
"A ti fi iṣẹlẹ naa to awọn ọlọpaa ati ileeṣẹ panapana leti, wọn si ti bẹrẹ iwadii lori ohun to sokunfa iṣẹlẹ ijamba ina naa."









