INEC: Òpómúléró ni ASUU jẹ́ fún àṣeyọrí ìbò 2019

Oríṣun àwòrán, INEC
Àwọn ọmọ ẹgbẹ́ ASUU ti gba láti kópa nínú ètò ìdìbò ọdún 2019.
Sáájú ní wọn ti ń dágúnla pé àwọn olùkọ́ ati akẹ́kọ́ọ̀ kò ní lè kópa nítorí ìyanṣẹ́lódì tó ń lọ lọ́wọ́.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
Ọjọ̀gbọ́n Mahmood Yakubu, alága INEC náà ti kédé pé, àwọn yóò ṣe ìpàdé pọ̀ pẹ̀lú ẹgbẹ́ ASUU.
Yakubu ni '' Eyi wa láti wa ojúùtú sí ọ̀rọ̀ ìyànṣẹ́lódì tó ń lọwọ́, sùgbọ́n ìpàdé náà kò ní kọjáa ọ̀rọ̀ nípa ìmúrasílẹ̀ fún ìdìbò gbogboogbo tó n bọ̀ nínú oṣù kejì ọdún"
" Ǹkan tó kàn wá jùlọ ní àwọn ipa pàtàkì tí àwọn olukọ tí INEC ti yan ní àwọn Fasiti láti kopa nínú ètò ìdìbò yoo ni.

A ti ní ìpinu pé ètò ìdìbò náà kò gbọdọ̀ ní kọ́nu-n-kọhọ nítori ìyanṣẹ́lodì àwọn oṣìṣẹ́ Fasiti. ASUU jẹ́ pàtàkì igun ilé fún àjọ wa láti ṣe ètò ìdìbo tó ṣe mú yangan láwujọ àwọn orílẹ̀-èdè.
À ń fojú sọ́nà fún ìpadé ti yóò mú àbájade rere jade wá "
Ẹwẹ̀, ìkéde pé àwọn yóò kopa yìí wáye lọjọ́ Jimọ, lẹ́yìn ìpàdé INEC àti ASUU.












