Àkọlé àwòrán, Eyi ni yoo jẹ aṣekagba ipolongo idibo gomina fun ẹgbẹ oṣelu APC
Alaga apapọ ẹgbẹ oṣelu APC, Adams Oshiomole ti fọrọ lede wipe mimu itesiwaju ba awọn iṣẹ rere ti ẹgbẹ naa ti fi lọlẹ nipinlẹ Ọṣun da lori ẹni ti yoo gba iṣakoso lọwọ gomina Rauf Arẹgbẹṣọla.
Oshiomole ṣe alaye ọrọ naa nibi asekagba ipolongo idibo ẹgbẹ oselu APC to waye lọjọ iṣẹgun, nilu Oṣogbo .
Adari ẹgbẹ osisẹ tẹlẹri ọhun fi kun ọrọ rẹ wipe ''ipinlẹ Ọṣun nilo ẹni to ni oye kikun ati ọgbọn atinuda nipa eto iṣejọba, yatọ si ẹni ti wọn ṣẹṣẹ n kọ.''
Àkọlé àwòrán, 'Ẹni ti a fa kalẹ yi ko kundun ode owanbẹ. Ko le ma a jo skelewu'
O tẹsiwaju wipe idi ti aare Muhammadu Buhari fi ba wọn peju-pesẹ sibi eto naa kii se fun itẹsiwaju isakoso ẹgbẹ oselu APC nikan, sugbọn lati fi da gbogbo eeyan ipinlẹ Ọṣun loju wipe ise rere ti egbe naa ti bẹrẹ yoo yọri.
O ni anfani ti Gboyega Oyetọla fi tayọ awọn oludije ti o ku ni oye ati iriri rẹ nipa eto iṣejọba.
Oríṣun àwòrán, Empics
Àkọlé àwòrán, Eyi ni yoo jẹ aṣekagba ipolongo idibo gomina fun ẹgbẹ oṣelu APC
Oshiomole tẹsiwaju wipe awọn eeyan ipinlẹ Ọṣun ko nilo gomina to kundun ode owanbẹ, tabi ẹni to fẹran ile ijo.
"Ẹni ti a fa kalẹ yi ko kundun ode owanbẹ. Ko le ma a jo skelewu.''
''Mo ranti wipe lọjọ diẹ sẹyin, wọn pe ipade itagbangba fun ifọrọwanilẹnu wo laarin awọn oludije si ipo gomina ipinlẹ Ọṣun, sugbọn ara ibi kọ lati yọọ ju sibẹ,nitori wipe o ti gba ijo lọ.''
A bí Moshood Olalekan Adeoti ni Ilú Ìwo, ijọba ibilẹ Iwo ní ìpínlẹ̀ Osun lọjọ́ kẹ́tàdínlogun oṣù kejì ọdún 1953
Ó bẹ̀rẹ̀ ilé ìwé alákọbẹ̀rẹ̀ ní District Council Primary Schoollọdun 1959 àti Aipate Day School lọdun 1964, lẹ́yìn náà ló lọ ilé ìwé Grammer lọdun 1974
Moshood Adeoti gboyè ìmọ ìṣòwò láti Fasiti Benin lọdún 1984
Moshood Olalekan Adeoti jẹ alága ẹgbẹ́ òṣèlú Alliance For Democracy 1998-2003, alága ẹgbẹ́ òṣèlú Action Congress 2006-2010 àti alága Action Congress of Nigeria ti alaga àkọkọ fún ẹgbk oselu APC 2010-2011
Isiaka Oyetola
All Progressives Congress (APC)
Kíni ọjọ́ ìbí yin?
Iṣẹ́ wo ni ẹ̀ ń ṣe?
Ìkádìí
Isiaka Adegboyega ti wọn bi ni ilu Iragbiji, ni ijọba ibilẹ Boripe ni ipinlẹ Ọsun.
Ọdun 1997 ni Oyetola ti darapọ mọ sise oselu, ati wipe o pẹlu awọn to da ẹgbẹ oselu Alliance for Democracy AD silẹ ni ọdun 1998.
Biotilẹjẹpe ogun ọdun niyi ti Oyetọla ti n se oselu, igba akọkọ ni yii ti yoo ma a dije du ipo labẹ ẹgbẹ oselu kan kan.
Amọ, iroyin kan ni wipe oun ni ẹyinoju Alaga Ẹgbẹ Oselu APC, Asiwaju Ahmed Tinubu ati Gomina Ipinlẹ Osun, Rauf Aregbesola
Alhaji Fatai Akinbade
African Democratic Congress (ADC)
Kíni ọjọ́ ìbí yin?
Iṣẹ́ wo ni ẹ̀ ń ṣe?
Ìkádìí
O darapọ mọ ilẹeṣẹ ijọba Ipinlẹ Ọṣun nibi to ti ṣiṣẹ fun ọdun mẹrindinlogun labẹ akoso ijọba oloogun mẹta ati ijọba alagbada Olagunsoye Oyinlọla.
Wọn yan Akinbade gẹgẹ bii akọwe ijọba Ipinlẹ Ọṣun nigba iṣakosi Olagunsoye Oyinlọla ni ọdun 2003.
O kede ipinnu rẹ lati gbe apoti ibo fun gomina ni ọdun 2010 laarin awọn oludije mẹrinla miiran, ṣugbọn ipinnu naa f'ori sanpọn.
Akinbade di oludije ẹgbẹ oṣelu ADC lẹyin ọsẹ meji to fi ẹgbẹ PDP silẹ.
Ademola Adeleke
People's Democratic Party (PDP)
Kíni ọjọ́ ìbí yin?
Iṣẹ́ wo ni ẹ̀ ń ṣe?
Ìkádìí
A bí Ademola Jackson Adeleke Ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù karún-un ọdún 1960 ní ìpínlẹ̀ Enugu ní ìdílé sínatọ̀ Raji Ayoola àti Nnena Esther Adeleke ní ìlú Ede
Ó lọ sí iléèwé alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ Methodist ní Surulere àti Nuwarudeen ní Ikire, bákan náà ló lọ iléèwé Seventh Day àti iléèwé Muslim Grammar ni ìlú Ede tí ó sì kọ́ ẹ̀kọ́ ìmọ̀ nípa ìwádìí ọ̀daràn ní Jacksonville State University Alabama USA.
Ó jẹ́ adarí àgbà ní iléeṣẹ́ Pacific Holdings Limited láti 2001 sí 2006 àti Quicksilver Courier Company ní Atlanta, Georgia láti 1985 sí 1989
Ademola Adeleke bẹ̀rẹ̀ òṣèlú ní ọdún 2007, ó sì dí sẹ́nétọ̀ tó ń sojú ẹkùn ìwọ̀-oòrùn Oṣun lẹ̀yìn ikú ẹgbọn rẹ̀ sẹ́nétọ̀ Isiaka Adeleke tó jẹ́ Gomìnà alágbádá àkọ́kọ́ ní ìpínlẹ̀ náà
Senator Iyiola Omisore
Social Democratic Party (SDP)
Kíni ọjọ́ ìbí yin?
Iṣẹ́ wo ni ẹ̀ ń ṣe?
Ìkádìí
Wọ́n bí Iyiọla Ajani Omisore sí ìdílé ọba ní ọjọ́ kẹẹ̀dógún, oṣù Kẹsàn án, ọdún 1957 ní ìlú Ilé-Ifẹ̀.
Omisore jẹ igbákejì gómìnà ìpínlẹ̀ Ọṣun, Adebisi Akande láàrin ọdún 1999- 2003.
Wọ́n dìbò yàn án sí ipò sẹ́nétọ̀ láti ṣojú ẹkùn ìdìbò ìlà oòrùn Ọṣun l'ábẹ́ àsìá ẹgbẹ́ òṣèlú PDP láàrin ọdún 2003 sí 2007, wọ́n tún padà dìbò yàn án ní 2007.
Ó díje fún ipò gómìnà ìpínlẹ̀ Ọṣun l'ọ́dún 2014 l'ábẹ́ àsìá ẹgbẹ́ òṣèlú Peoples Democratic Party, PDP, sùgbọ́n Rauf Aregbẹsọla fi ẹ̀yìn rẹ̀ janlẹ̀ nínú ètò ìdìbò nàá tó wáyé ní ọjọ́ kẹsàn án, oṣù Kẹjọ 2014.
Wo àwọn olùdíje
Ìkádìí
Oríṣun àwòrán, @NajeemFSalaam
Àkọlé àwòrán, Awọn Gomina ẹgbẹ APC naa wa gbaruku ti akẹgbẹ wọn Rauf Aregbesola nibi ipolongo ohun
O rọ awọn eeyan ipinlẹ Ọṣun lati jade dibo wọn fun ẹgbẹ oṣelu APC lọjọ kejilelogun oṣu kẹẹsan ọdun yi, ki oṣẹ rere ẹgbẹ naa le tẹsiwaju.Ipolongo eto idibo naa ni aṣejagba iruẹ fun ẹgbẹ oṣelu APC saaju eto idibo si ipo gomina ti yoo waye ni ipinlẹ naa.
Àkọlé àwòrán, Ni ipari ipolongo naa wọn gbe asia ẹgbẹ fun Gboyega Oyetọla
Lara awọn eekan to ba wọn peju-lesẹ nibi akanṣe eto naa ni aare Muhammadu Buhari, adari ẹgbẹ oṣelu naa, Bola Ahmed Tinubu, Minisita fun ikansira ẹni, Adebayọ Shittu, minisita fun eto ilera Isaac Adewole, ati bẹẹbẹẹ lọ
Àkọlé àwòrán, Bola Tinubu,Adams Osiomole ati awon eekan ẹgbẹ wa lara awọn to peju sibẹ .