Ekiti 2018: Igbákejì Gómìnà ṣèlérí ìtẹ̀síwájú kébi-má-pàlú

Ọbẹ̀ ẹ̀fọ́

Oríṣun àwòrán, @matsecooks

Àkọlé àwòrán, Fayose gbe ètò olóògùn ebi "Stomach infrastructure" kalẹ ni ibẹrẹ saa keji iṣejọba rẹ
Àkọlé fídíò, È gbọ àlàyé lẹnu àwọn ti ójúẹlẹgba leko irú iṣẹ ti oògùn olóró má n ṣé lara.

Eto oloogun ebi yoo tẹsiwaju lẹyin iṣejọba Gomina Ayodele Fayose.Oludije fun ipo gomina ipinlẹ Ekiti labẹ aṣia ẹgbẹ oṣelu Peoples Democratic Party, PDP, Ọjọgbọn Kọlapọ Oluṣọla Eleka, lo ṣeleri yii, lasiko ti o n ba awọn oṣiṣẹ kan sọrọ nilu Ado Ekiti.

Eto "oloogun ebi" eleyi ti adape rẹ lede Gẹẹsi jẹ "stomach infrastructure" ni gomina Fayose gbe kalẹ ni ibẹrẹ saa keji iṣejọba rẹ, eyi to si da ọpọlọpọ họwu-họwu silẹ nigba naa.

Iṣọla Eleka
Àkọlé àwòrán, Eleka ni ko si ohun to buru ninu ka bu irẹsi igba Naira, ati ẹwa diẹ fun araalu lati fi gbenuro

Iṣọla Eleka to tun jẹ igbakeji ijọba to n kogba wọle lọwọ nipinlẹ Ekiti sọ pe atunṣe ranpẹ yoo ba eto naa eleyi ti yoo gbee kuro ni anfani ipinlẹ nikan lọ si awọn ẹka ijọba ibilẹ gbogbo to wa l'Ekiti.

Amin iyasọtọ kan

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Àkọlé fídíò, Plateau: Àsìkó tó láti fi káádì ìdìbò yanjú ọ̀rọ̀ Buhari
Àkọlé fídíò, Ijamba ina Eko; Awakọ ni omi gọta lo yọ oun ninu ijamba ina