APC: Ọ̀rọ̀ àbùkù látẹnu Okorocha ń ta ẹrẹ̀ bá ẹgbẹ́ wa

Oríṣun àwòrán, @ImoGovernor
Nkan kò lọ déédé láàrín ìgbìmọ̀ aláṣẹ ẹgbẹ́ òṣèlú APC àti Gomina Ìpínlẹ̀ Imo, Rochas Okorocha, lórí àwọn ọ̀rọ̀ kan tí wọ́n ní ó ń tẹnu rẹ̀ jáde.
Atẹ̀jáde kan láti ọwọ́ alukoro ẹgbẹ́ òsèlú APC, Bolaji Abdullahi, sọ pé, lẹ́nu ọjọ́ mẹ́ta yìí ni Okorocha ń sọrọ àbùkù sí ẹgbẹ́ nàá, àwọn àgbààgbà ẹgbẹ́ àti alaga wọn, Olóyè John Odigie-Oyegun lórí ìdìbò abẹ́le tí ó wáyé ní oṣù karùń-un ní ìpínlẹ̀ Imo.
Okorocha, tó jẹ́ alága ìgbìmọ̀ àwọn gómínà APC ni wọ́n ní ó lo ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ kan tí orúkọ rẹ̀ ńjẹ́ Ireagwu Obioma láti gbé àtẹ̀jáde kan jáde tí ó fẹ̀sùn oríṣiríṣi kan ẹgbẹ́ APC.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
Àwọn òǹwòye ní, ọ̀rọ̀ náà jẹ àbùkù fún ìṣọkan APC nítori ipò tí Okorocha wà nínú ẹgbẹ́ nàá láti ilẹ̀ wá.

Oríṣun àwòrán, @ImoGovernor
Atẹ̀jáde ẹgbẹ́ náà tilẹ̀ fi ẹ̀sùn kán pé, o gbé ìwé kan jáde nínú èyí tí wọ́n lo ayédèru orúkọ àwọn olọ́yè ẹgbẹ́ nàá méjì - Edwin Ikhinmwin àti amòfin agbà Muiz Banire.
Ẹgbẹ́ APC ní, àwọn kò ní gba ọ̀rọ̀-kọ́rọ̀ láàyè nínú ẹgbẹ́ náà o. Wọ́n wa rọ Okorocha láti kó ara rẹ̀ ní ìjánu, kí ó sì wá ọ̀nà àlàáfíà pẹ̀lú àwọn àgbààgbà ẹgbẹ́ náà.








