Ìfòyà ní Maiduguri bí Boko Haram ṣe ti ya wọ Bárékè

Abubakar Shekau

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Àkọlé àwòrán, Ọmọ ogun Nàíjírà ń kojú Boko Haram ní àríwá ìlà ooòrùn
Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 1

Ìròyìn tó ń tẹ̀ wá lọ́wọ́ láti ìlú Maiduguri ní ìpínlè Bornu ló ń sọ pé àwọn afẹ̀míṣòfò Boko Haram, ti ya wọ bárékè Giwa àwọn ológun ní ìlú náà.

Ọ̀rọ̀ ti di bóòlọ-o-yà-mi, báyìí ní agbègbè tí bárékè náà wà lẹ̀yìn tí àwọn Boko Haram dojú ìjà kọ àwọn ọmọ oogun ilẹ̀ Naijiria.

DSP Edet Okon, to jẹ́ agbẹnusọ fún àwọn ọlọ́pàá, tí ó bá ilé isẹ́ BBC Yoruba sọ̀rọ̀ fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé nkàn kò fara rọ báyìí ní ìlú Maiduguri.

Àwọn ará àdugbò bárékè náà sọ lórì Twitter wí pé àwọn ti ń gbọ́ ìró ìbọn látàárọ̀.

Skip X post, 1
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 1

Ó dàbí pé àwọn ọmọ ogun ilẹ̀ ti gbé ìgbésè nítorí ọkọ̀ òfurufú ti ń fò kiri, tí ìró ìbọ̀n sì ti ń dínkù

Skip X post, 2
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 2

Àwọn ológun kò tíì sọ̀rọ̀ lórí ìsẹ̀lẹ̀ náà.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Àkọlé fídíò, Àìsàn ibà; Àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀ nípa lílo ewé áti egbò